Add parallel Print Page Options

Ègbé ni fún àwọn tí o gbẹ́kẹ̀lé Ejibiti

31 Ègbé ni fún àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí
    Ejibiti fún ìrànlọ́wọ́,
tí wọn gbẹ́kẹ̀lé ẹṣin
    tí wọ́n fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ kẹ̀kẹ́-ẹṣin wọn
àti agbára ńlá àwọn ẹlẹ́ṣin wọn,
    ṣùgbọ́n tiwọn kò bojú wo Ẹni Mímọ́ Israẹli n nì,
    tàbí kí wọn wá ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Olúwa.
Síbẹ̀síbẹ̀ òun pẹ̀lú jẹ́ ọlọ́gbọ́n ó sì lè mú ìparun wá;
    òun kì í kó ọ̀rọ̀ rẹ̀ jẹ.
Òun yóò dìde sí ilé àwọn ìkà,
    àti sí àwọn tí ń ṣe ìrànlọ́wọ́ fún aṣebi.
Ṣùgbọ́n ènìyàn lásán ni àwọn ará Ejibiti
    wọn kì í ṣe Ọlọ́run;
ẹran-ara ni àwọn ẹṣin wọn, kì í ṣe ẹ̀mí.
    Nígbà tí Olúwa bá na ọwọ́ rẹ̀ jáde,
ẹni náà tí ó ń ṣèrànwọ́ yóò kọsẹ̀,
    ẹni náà tí à ń ràn lọ́wọ́ yóò ṣubú;
    àwọn méjèèjì yóò sì jùmọ̀ parun.

Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi:

“Gẹ́gẹ́ bí i kìnnìún ti í ké
    àní kìnnìún ńlá lórí ẹran ọdẹ rẹ̀
bí a tilẹ̀ rí ẹgbẹ́ àwọn olùṣọ́-àgùntàn
    tí a sì pè wọ́n papọ̀ láti kojú rẹ̀,
ẹ̀rù kò lè bà á pẹ̀lú igbe wọn
    akitiyan wọn kò sì lè dí i lọ́wọ́
bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò sọ̀kalẹ̀ wá
    láti jagun lórí òkè Sioni àti lórí ibi gíga rẹ̀.
Gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹyẹ ti ń rábàbà lókè
    Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò dáàbò bo Jerusalẹmu,
Òun yóò dáàbò bò ó yóò sì tú u sílẹ̀
    Òun yóò ré e kọjá yóò sì gbà á sílẹ̀.”

Ẹ padà sọ́dọ̀ ẹni tí ẹ ti ṣọ̀tẹ̀ sí gidigidi, Ẹ̀yin ọmọ Israẹli.

Nítorí ní ọjọ́ náà, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín yóò kọ àwọn ère fàdákà àti wúrà tí ọwọ́ ẹ̀ṣẹ̀ yín ti ṣe.
“Asiria yóò ṣubú lọ́wọ́ idà kan tí kò ti ọwọ́ ènìyàn wá;
    idà tí kì í ṣe ti ẹ̀dá alààyè ni yóò pa wọ́n.
Wọn yóò sì sá níwájú idà náà
    àti àwọn ọmọkùnrin wọn ni a ó fún ní iṣẹ́ ipá ṣe.
Àpáta rẹ yóò kọjá lọ fún ẹ̀rù;
    àwọn olórí rẹ yóò bẹ̀rù asia náà,”
    ni Olúwa wí,
ẹni tí iná rẹ̀ ń bẹ ní Sioni,
    ẹni tí ìléru rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu.

Woe to Those Who Rely on Egypt

31 Woe(A) to those who go down to Egypt(B) for help,
    who rely on horses,(C)
who trust in the multitude of their chariots(D)
    and in the great strength of their horsemen,
but do not look to the Holy One(E) of Israel,
    or seek help from the Lord.(F)
Yet he too is wise(G) and can bring disaster;(H)
    he does not take back his words.(I)
He will rise up against that wicked nation,(J)
    against those who help evildoers.
But the Egyptians(K) are mere mortals and not God;(L)
    their horses(M) are flesh and not spirit.
When the Lord stretches out his hand,(N)
    those who help will stumble,
    those who are helped(O) will fall;
    all will perish together.(P)

This is what the Lord says to me:

“As a lion(Q) growls,
    a great lion over its prey—
and though a whole band of shepherds(R)
    is called together against it,
it is not frightened by their shouts
    or disturbed by their clamor(S)
so the Lord Almighty will come down(T)
    to do battle on Mount Zion and on its heights.
Like birds hovering(U) overhead,
    the Lord Almighty will shield(V) Jerusalem;
he will shield it and deliver(W) it,
    he will ‘pass over’(X) it and will rescue it.”

Return,(Y) you Israelites, to the One you have so greatly revolted(Z) against. For in that day(AA) every one of you will reject the idols of silver and gold(AB) your sinful hands have made.(AC)

“Assyria(AD) will fall by no human sword;
    a sword, not of mortals, will devour(AE) them.
They will flee before the sword
    and their young men will be put to forced labor.(AF)
Their stronghold(AG) will fall because of terror;
    at the sight of the battle standard(AH) their commanders will panic,(AI)
declares the Lord,
    whose fire(AJ) is in Zion,
    whose furnace(AK) is in Jerusalem.