Add parallel Print Page Options

30 “Ègbé ni àwọn ọmọ fún orílẹ̀-èdè alágídí,”
    ni Olúwa wí,
“Fún àwọn tí ó gbé ètò jáde tí kì í ṣe tèmi,
    tí wọ́n ń gbìmọ̀ pọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa Ẹ̀mí mi,
    tí wọ́n ń dá ẹ̀ṣẹ̀ lórí ẹ̀ṣẹ̀;
tí wọ́n lọ sí Ejibiti
    láìṣe fún mi,
tí ó ń wá ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Farao fún ààbò,
    sí òjìji Ejibiti fún ibi ìsádi.
Ṣùgbọ́n ààbò Farao yóò jásí ìtìjú fún un yín,
    òjìji Ejibiti yóò mú àbùkù bá a yín.
Bí àwọn olórí rẹ tilẹ̀ wà ní Ṣoani,
    tí àwọn ikọ̀ wọn sì ti dé sí Hanisi,
gbogbo wọn ni a ó dójútì,
    nítorí àwọn ènìyàn kan tí kò wúlò fún wọn,
tí kò mú ìrànlọ́wọ́ tàbí àǹfààní wá,
    bí kò ṣe àbùkù àti ìdójúti ni.”

Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ sí àwọn ẹranko tí ó wà ní gúúsù:

Láàrín ilẹ̀ ìnira àti ìpọ́njú,
    ti kìnnìún àti abo kìnnìún
ti paramọ́lẹ̀ àti ejò olóró,
    àwọn ikọ̀ náà kó ẹrù àti ọrọ̀
wọn lẹ́yìn àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,
    àwọn ohun ìní wọn ní orí àwọn ìbákasẹ,
    sí orílẹ̀-èdè aláìlérè,
sí Ejibiti tí ìrànlọ́wọ́ rẹ̀
    kò wúlò rárá.
Nítorí náà mo pè é ní
    Rahabu aláìlẹ́ṣẹ̀ nǹkan kan.

Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọ ọ́ sí ara wàláà fún wọn,
    tẹ̀ ẹ́ sí ara ìwé kíká,
pé fún àwọn ọjọ́ tí ó ń bọ̀
    kí ó sì lè jẹ́ ẹ̀rí ayérayé.
Àwọn wọ̀nyí jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn
    àti ẹlẹ́tanu ọmọ,
àwọn ọmọ tí wọn kò ṣetán láti tẹ́tí sí
    ìtọ́ni Olúwa.
10 Wọ́n sọ fún àwọn aríran pé,
    “Ẹ má ṣe rí ìran mọ́!”
Àti fún àwọn wòlíì,
    “Ẹ má ṣe fi ìran ohun tí ó tọ́ hàn wá mọ́!
Ẹ sọ ohun tí ó tura fún wa,
    ẹ sàsọtẹ́lẹ̀ ẹ̀tàn.
11 Ẹ fi ọ̀nà yìí sílẹ̀,
    ẹ kúrò ní ọ̀nà yìí
ẹ dẹ́kun à ń dojú ìjà kọ wá
    pẹ̀lú Ẹni Mímọ́ Israẹli!”

12 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ẹni Mímọ́ Israẹli wí:

“Nítorí pé ẹ ti kọ ọ̀rọ̀ yìí sílẹ̀,
    ẹ gbára lé ìnilára
    kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé ẹ̀tàn,
13 ẹ̀ṣẹ̀ yìí yóò rí fún ọ
    gẹ́gẹ́ bí ògiri gíga, tí ó sán tí ó sì fì
    tí ó sì wó lójijì, àti ní ìṣẹ́jú kan.
14 Yóò sì fọ́ ọ sí wẹ́wẹ́ bí àpáàdì
    tí a fọ́ pátápátá
àti pé a kò ní rí ẹ̀rún kan nínú àfọ́kù rẹ̀,
    fún mímú èédú kúrò nínú ààrò
    tàbí gbígbọ́n omi jáde kúrò nínú àmù.”

15 Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli wí:

“Nínú ìrònúpìwàdà àti ìsinmi ni ìgbàlà rẹ wà,
    ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ àti ìgbẹ́kẹ̀lé ni agbára rẹ wà,
    ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò ní ọ̀kankan nínú wọn.
16 Ẹ̀yin wí pé, ‘bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò sálọ lórí ẹṣin.’
    Nítorí náà ẹ̀yin yóò sá!
Ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa yóò gun àwọn ẹṣin tí ó yára lọ.’
    Nítorí náà àwọn tí ń lé e yín yóò yára!
17 Ẹgbẹ̀rún yóò sá
    nípa ìdẹ́rùbà ẹnìkan;
nípa ìdẹ́rùbà ẹni márùn-ún
    gbogbo yín lẹ ó sálọ,
títí a ó fi yín sílẹ̀
    àti gẹ́gẹ́ bí igi àsíá ní orí òkè,
    gẹ́gẹ́ bí àsíá lórí òkè.”

18 Síbẹ̀síbẹ̀ Olúwa sì fẹ́ ṣíjú àánú wò ọ́;
    ó dìde láti ṣàánú fún ọ.
Nítorí Olúwa jẹ́ Ọlọ́run ìdájọ́.
    Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó dúró dè é!

19 Ẹ̀yin ènìyàn Sioni, tí ń gbé ní Jerusalẹmu, ìwọ kì yóò sọkún mọ́. Báwo ni àánú rẹ̀ yóò ti pọ̀ tó nígbà tí ìwọ bá kígbe fún ìrànlọ́wọ́! Bí ó bá ti gbọ́, òun yóò dá ọ lóhùn. 20 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa fún ọ ní àkàrà ìyà àti omi ìpọ́njú, àwọn olùkọ́ rẹ kì yóò fi ara sin mọ́; pẹ̀lú ojú rẹ ni ìwọ ó rí wọn. 21 Bí o bá yí sápá ọ̀tún tàbí apá òsì, etí rẹ yóò máa gbọ́ ohùn kan lẹ́yìn rẹ, wí pé, “Ọ̀nà nìyìí, máa rìn nínú rẹ̀.” 22 Lẹ́yìn náà ni ẹ ó ba àwọn ère yín jẹ́ àwọn tí ẹ fi fàdákà bò àti àwọn ère tí ẹ fi wúrà bò pẹ̀lú, ẹ ó sọ wọ́n nù bí aṣọ tí obìnrin fi ṣe nǹkan oṣù ẹ ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ kúrò níbí!”

23 Òun yóò sì rọ òjò fún un yín sí àwọn irúgbìn tí ẹ gbìn sórí ilẹ̀, oúnjẹ tí yóò ti ilẹ̀ náà wá yóò ní ọ̀rá yóò sì pọ̀. Ní ọjọ́ náà ni àwọn ẹran ọ̀sìn yín yóò máa jẹ koríko ní pápá oko tútù tí ó tẹ́jú. 24 Àwọn màlúù àti àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó ń tú ilẹ̀ yóò jẹ oúnjẹ àdídùn tí a fi àmúga àti ṣọ́bìrì fọ́nkálẹ̀. 25 Ní ọjọ́ tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò sọ ẹ̀mí wọn nù nígbà tí ilé ìṣọ́ yóò wó lulẹ̀, odò omi yóò sàn lórí òkè gíga àti lórí àwọn òkè kékeré. 26 Òṣùpá yóò sì tàn bí oòrùn, àti ìtànṣán oòrùn yóò mọ́lẹ̀ ní ìlọ́po méje, gẹ́gẹ́ bí ìmọ́lẹ̀ odidi ọjọ́ méje, nígbà tí Olúwa yóò di ojú ọgbẹ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ tí yóò sì wo ọgbẹ́ tí ó ti dá sí wọn lára sàn.

27 Kíyèsi i, orúkọ Olúwa ti òkèèrè wá
    pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti kurukuru
èéfín tí ó nípọn;
    ètè rẹ̀ kún fún ìbínú
    ahọ́n rẹ̀ sì jẹ́ iná ajónirun.
28 Èémí rẹ̀ sì dàbí òjò alágbára,
    tí ó rú sókè dé ọ̀run.
Ó jọ àwọn orílẹ̀-èdè nínú kọ̀ǹkọ̀sọ̀;
    ó sì fi sí ìjánu ní àgbọ̀n àwọn ènìyàn
    láti ṣì wọ́n lọ́nà.
29 Ẹ̀yin ó sì kọrin
    gẹ́gẹ́ bí i ti alẹ́ tí ẹ̀ ń ṣe àjọyọ̀ àpéjọ mímọ́,
ọkàn yín yóò yọ̀
    gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí àwọn ènìyàn gòkè lọ pẹ̀lú fèrè
sí orí òkè Olúwa,
    àní sí àpáta Israẹli.
30 Olúwa yóò jẹ́ kí wọn ó gbọ́ ohùn ògo rẹ̀
    yóò sì jẹ́ kí wọ́n rí apá rẹ̀ tí ó ń bọ̀ wálẹ̀
pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti iná ajónirun,
    pẹ̀lú mọ̀nàmọ́ná, àrá àti yìnyín.
31 Ohùn Olúwa yóò fọ́ Asiria túútúú,
    pẹ̀lú ọ̀pá aládé rẹ̀ ni yóò lù wọ́n bolẹ̀.
32 Ẹgba kọ̀ọ̀kan tí Olúwa bá gbé lé wọn
    pẹ̀lú ọ̀pá ìjẹníyà rẹ̀
yóò jẹ́ ti ṣaworo àti ti dùùrù,
    gẹ́gẹ́ bí ó ti ń bá wọn jà lójú ogun
    pẹ̀lú ìkùùkuu láti apá rẹ̀.
33 A ti tọ́jú Tofeti sílẹ̀ tipẹ́tipẹ́,
    a ti tọ́jú rẹ̀ sílẹ̀ fún ọba.
Ojú ààrò rẹ̀ ni a ti gbẹ́ jì tí ó sì fẹ̀,
    pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ iná àti igi ìdáná;
èémí Olúwa,
    gẹ́gẹ́ bí ìṣàn sulfuru ń jó ṣe mú un gbiná.

Woe to the Obstinate Nation

30 “Woe(A) to the obstinate children,”(B)
    declares the Lord,
“to those who carry out plans that are not mine,
    forming an alliance,(C) but not by my Spirit,
    heaping sin upon sin;
who go down to Egypt(D)
    without consulting(E) me;
who look for help to Pharaoh’s protection,(F)
    to Egypt’s shade for refuge.(G)
But Pharaoh’s protection will be to your shame,
    Egypt’s shade(H) will bring you disgrace.(I)
Though they have officials in Zoan(J)
    and their envoys have arrived in Hanes,
everyone will be put to shame
    because of a people(K) useless(L) to them,
who bring neither help(M) nor advantage,
    but only shame and disgrace.(N)

A prophecy(O) concerning the animals of the Negev:(P)

Through a land of hardship and distress,(Q)
    of lions(R) and lionesses,
    of adders and darting snakes,(S)
the envoys carry their riches on donkeys’(T) backs,
    their treasures(U) on the humps of camels,
to that unprofitable nation,
    to Egypt, whose help is utterly useless.(V)
Therefore I call her
    Rahab(W) the Do-Nothing.

Go now, write it on a tablet(X) for them,
    inscribe it on a scroll,(Y)
that for the days to come
    it may be an everlasting witness.(Z)
For these are rebellious(AA) people, deceitful(AB) children,
    children unwilling to listen to the Lord’s instruction.(AC)
10 They say to the seers,(AD)
    “See no more visions(AE)!”
and to the prophets,
    “Give us no more visions of what is right!
Tell us pleasant things,(AF)
    prophesy illusions.(AG)
11 Leave this way,(AH)
    get off this path,
and stop confronting(AI) us
    with the Holy One(AJ) of Israel!”

12 Therefore this is what the Holy One(AK) of Israel says:

“Because you have rejected this message,(AL)
    relied on oppression(AM)
    and depended on deceit,
13 this sin will become for you
    like a high wall,(AN) cracked and bulging,
    that collapses(AO) suddenly,(AP) in an instant.
14 It will break in pieces like pottery,(AQ)
    shattered so mercilessly
that among its pieces not a fragment will be found
    for taking coals from a hearth
    or scooping water out of a cistern.”

15 This is what the Sovereign(AR) Lord, the Holy One(AS) of Israel, says:

“In repentance and rest(AT) is your salvation,
    in quietness and trust(AU) is your strength,
    but you would have none of it.(AV)
16 You said, ‘No, we will flee(AW) on horses.’(AX)
    Therefore you will flee!
You said, ‘We will ride off on swift horses.’
    Therefore your pursuers will be swift!
17 A thousand will flee
    at the threat of one;
at the threat of five(AY)
    you will all flee(AZ) away,
till you are left(BA)
    like a flagstaff on a mountaintop,
    like a banner(BB) on a hill.”

18 Yet the Lord longs(BC) to be gracious to you;
    therefore he will rise up to show you compassion.(BD)
For the Lord is a God of justice.(BE)
    Blessed are all who wait for him!(BF)

19 People of Zion, who live in Jerusalem, you will weep no more.(BG) How gracious he will be when you cry for help!(BH) As soon as he hears, he will answer(BI) you. 20 Although the Lord gives you the bread(BJ) of adversity and the water of affliction, your teachers(BK) will be hidden(BL) no more; with your own eyes you will see them. 21 Whether you turn to the right or to the left, your ears will hear a voice(BM) behind you, saying, “This is the way;(BN) walk in it.” 22 Then you will desecrate your idols(BO) overlaid with silver and your images covered with gold;(BP) you will throw them away like a menstrual(BQ) cloth and say to them, “Away with you!(BR)

23 He will also send you rain(BS) for the seed you sow in the ground, and the food that comes from the land will be rich(BT) and plentiful.(BU) In that day(BV) your cattle will graze in broad meadows.(BW) 24 The oxen(BX) and donkeys that work the soil will eat fodder(BY) and mash, spread out with fork(BZ) and shovel. 25 In the day of great slaughter,(CA) when the towers(CB) fall, streams of water will flow(CC) on every high mountain and every lofty hill. 26 The moon will shine like the sun,(CD) and the sunlight will be seven times brighter, like the light of seven full days, when the Lord binds up the bruises of his people and heals(CE) the wounds he inflicted.

27 See, the Name(CF) of the Lord comes from afar,
    with burning anger(CG) and dense clouds of smoke;
his lips are full of wrath,(CH)
    and his tongue is a consuming fire.(CI)
28 His breath(CJ) is like a rushing torrent,(CK)
    rising up to the neck.(CL)
He shakes the nations in the sieve(CM) of destruction;
    he places in the jaws of the peoples
    a bit(CN) that leads them astray.
29 And you will sing
    as on the night you celebrate a holy festival;(CO)
your hearts will rejoice(CP)
    as when people playing pipes(CQ) go up
to the mountain(CR) of the Lord,
    to the Rock(CS) of Israel.
30 The Lord will cause people to hear his majestic voice(CT)
    and will make them see his arm(CU) coming down
with raging anger(CV) and consuming fire,(CW)
    with cloudburst, thunderstorm(CX) and hail.(CY)
31 The voice of the Lord will shatter Assyria;(CZ)
    with his rod he will strike(DA) them down.
32 Every stroke the Lord lays on them
    with his punishing club(DB)
will be to the music of timbrels(DC) and harps,
    as he fights them in battle with the blows of his arm.(DD)
33 Topheth(DE) has long been prepared;
    it has been made ready for the king.
Its fire pit has been made deep and wide,
    with an abundance of fire and wood;
the breath(DF) of the Lord,
    like a stream of burning sulfur,(DG)
    sets it ablaze.(DH)