Add parallel Print Page Options

Orin ìyìn kan

26 Ní ọjọ́ náà ni a ó kọ orin yìí ní ilẹ̀ Juda:

Àwa ní ìlú alágbára kan,
    Ọlọ́run fi ìgbàlà ṣe
    ògiri àti ààbò rẹ̀.
Ṣí àwọn ìlẹ̀kùn
    kí àwọn olódodo orílẹ̀-èdè kí ó lè wọlé,
    orílẹ̀-èdè tí ó pa ìgbàgbọ́ mọ́.
Ìwọ yóò pa á mọ́ ní àlàáfíà pípé
    ọkàn ẹni tí ó dúró ṣinṣin,
    nítorí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa títí láé,
    nítorí Olúwa, Olúwa ni àpáta
    ayérayé náà.
Ó sọ àwọn tí ó ń gbé ní òkè di onírẹ̀lẹ̀
    ó rẹ ìlú agbéraga náà nílẹ̀;
ó sọ ọ́ di ilẹ̀ pẹrẹsẹ
    ó sì sọ ọ́ sílẹ̀ nínú erùpẹ̀.
Ẹsẹ̀ tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀
    ẹsẹ̀ aninilára n nì,
    ipasẹ̀ àwọn òtòṣì.

Ipa ọ̀nà àwọn olódodo tẹ́jú
    Ìwọ tó dúró ṣinṣin, ìwọ mú ọ̀nà
    àwọn olódodo ṣe geere.
Bẹ́ẹ̀ ni, Olúwa, rírìn ní ọ̀nà òfin rẹ
    àwa dúró dè ọ́;
orúkọ rẹ àti òkìkí rẹ
    àwọn ni ohun tí ọkàn wa ń fẹ́.
Ọkàn mi ń pòùngbẹẹ̀ rẹ ní ọ̀gànjọ́ òru;
    ní òwúrọ̀ ni ẹ̀mí mi ń ṣàfẹ́rí rẹ.
Nígbà tí ìdájọ́ rẹ bá sọ̀kalẹ̀ sórí ayé
    àwọn ènìyàn yóò kọ́ ìṣòdodo.
10 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a fi oore-ọ̀fẹ́ hàn sí àwọn ìkà
    wọn kò kọ́ láti sọ òdodo;
kódà ní ilẹ̀ àwọn tí ó dúró ṣinṣin wọ́n
    tẹ̀síwájú láti máa ṣe ibi
    wọn kò sì ka ọláńlá Olúwa sí.
11 Olúwa, ti gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè
    ṣùgbọ́n àwọn kò rí i.
Jẹ́ kí wọ́n rí ìtara rẹ fún àwọn ènìyàn rẹ
    kí ojú kí ó tì wọ́n;
jẹ́ kí iná tí a fi pamọ́ fún àwọn
    ọ̀tá rẹ jó wọn run.

12 Olúwa, ìwọ fi àlàáfíà lélẹ̀ fún wa;
    ohun gbogbo tí a ti ṣe yọrí ìwọ ni
    ó ṣe é fún wa.
13 Olúwa Ọlọ́run wa, àwọn olúwa mìíràn
    lẹ́yìn rẹ ti jẹ ọba lé wa lórí,
    ṣùgbọ́n orúkọ rẹ nìkan ni àwa fi ọ̀wọ̀ fún.
14 Wọ́n ti kú báyìí, wọn ò sí láààyè mọ́;
    gbogbo ẹ̀mí tí ó ti kọjá lọ wọ̀nyí kò le dìde mọ́.
Ìwọ jẹ́ wọ́n ní ìyà o sì sọ wọ́n di asán,
    Ìwọ pa gbogbo ìrántí wọn rẹ́ pátápátá.
15 Ìwọ ti mú orílẹ̀-èdè gbòòrò, Olúwa;
    ìwọ ti mú orílẹ̀-èdè bí sí i.
Ìwọ ti gba ògo fún ara rẹ;
    ìwọ ti sún gbogbo àwọn ààlà ilẹ̀ sẹ́yìn.

16 Olúwa, wọ́n wá sọ́dọ̀ rẹ nínú ìpọ́njú wọn;
    nígbà tí ìbáwí rẹ wà lára wọn,
    wọ́n gbàdúrà kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́.
17 Gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó lóyún tí ó sì fẹ́rẹ̀ bímọ
    tí í rúnra tí ó sì ń sọkún nínú ìrora rẹ̀,
    bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwa rí níwájú rẹ Olúwa.
18 Àwa wà nínú oyún, a wà nínú ìrora
    ṣùgbọ́n, afẹ́fẹ́ ni a bí lọ́mọ.
Àwa kò mú ìgbàlà wá sí ilẹ̀ ayé;
    àwa kọ́ ni a bí àwọn ènìyàn tí ó wà láyé.

19 Ṣùgbọ́n àwọn òkú yín yóò wà láààyè
    ara wọn yóò dìde.
Ìwọ tí o wà nínú erùpẹ̀,
    dìde nílẹ̀ kí o sì ké igbe ayọ̀.
Ìrì rẹ dàbí ìrì òwúrọ̀,
    ayé yóò bí àwọn òkú rẹ̀ lọ́mọ.

20 Ẹ lọ, ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ wọ ìyẹ̀wù yín lọ
    kí ẹ sì ti àwọn ìlẹ̀kùn lẹ́yìn yín,
ẹ fi ara yín pamọ́ fún ìgbà díẹ̀
    títí tí ìbínú rẹ̀ yóò fi rékọjá.
21 Kíyèsi i, Olúwa ń jáde bọ̀ láti ibùgbé rẹ̀
    láti jẹ àwọn ènìyàn ilẹ̀ ayé ní
ìyà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
    Ayé yóò sì sọ àwọn ẹ̀jẹ̀ tí a ta sí orí rẹ̀,
    kì yóò sì fi àwọn tí a ti pa pamọ́ mọ́.

A Song of Praise

26 In that day(A) this song will be sung(B) in the land of Judah:

We have a strong city;(C)
    God makes salvation
    its walls(D) and ramparts.(E)
Open the gates(F)
    that the righteous(G) nation may enter,
    the nation that keeps faith.
You will keep in perfect peace(H)
    those whose minds are steadfast,
    because they trust(I) in you.
Trust(J) in the Lord forever,(K)
    for the Lord, the Lord himself, is the Rock(L) eternal.
He humbles those who dwell on high,
    he lays the lofty city low;
he levels it to the ground(M)
    and casts it down to the dust.(N)
Feet trample(O) it down—
    the feet of the oppressed,(P)
    the footsteps of the poor.(Q)

The path of the righteous is level;(R)
    you, the Upright One,(S) make the way of the righteous smooth.(T)
Yes, Lord, walking in the way of your laws,[a](U)
    we wait(V) for you;
your name(W) and renown
    are the desire of our hearts.
My soul yearns for you in the night;(X)
    in the morning my spirit longs(Y) for you.
When your judgments(Z) come upon the earth,
    the people of the world learn righteousness.(AA)
10 But when grace is shown to the wicked,(AB)
    they do not learn righteousness;
even in a land of uprightness they go on doing evil(AC)
    and do not regard(AD) the majesty of the Lord.
11 Lord, your hand is lifted high,(AE)
    but they do not see(AF) it.
Let them see your zeal(AG) for your people and be put to shame;(AH)
    let the fire(AI) reserved for your enemies consume them.

12 Lord, you establish peace(AJ) for us;
    all that we have accomplished you have done(AK) for us.
13 Lord our God, other lords(AL) besides you have ruled over us,
    but your name(AM) alone do we honor.(AN)
14 They are now dead,(AO) they live no more;
    their spirits(AP) do not rise.
You punished them and brought them to ruin;(AQ)
    you wiped out all memory of them.(AR)
15 You have enlarged the nation, Lord;
    you have enlarged the nation.(AS)
You have gained glory for yourself;
    you have extended all the borders(AT) of the land.

16 Lord, they came to you in their distress;(AU)
    when you disciplined(AV) them,
    they could barely whisper(AW) a prayer.[b]
17 As a pregnant woman about to give birth(AX)
    writhes and cries out in her pain,
    so were we in your presence, Lord.
18 We were with child, we writhed in labor,
    but we gave birth(AY) to wind.
We have not brought salvation(AZ) to the earth,
    and the people of the world have not come to life.(BA)

19 But your dead(BB) will live, Lord;
    their bodies will rise—
let those who dwell in the dust(BC)
    wake up and shout for joy—
your dew(BD) is like the dew of the morning;
    the earth will give birth to her dead.(BE)

20 Go, my people, enter your rooms
    and shut the doors(BF) behind you;
hide(BG) yourselves for a little while
    until his wrath(BH) has passed by.(BI)
21 See, the Lord is coming(BJ) out of his dwelling(BK)
    to punish(BL) the people of the earth for their sins.
The earth will disclose the blood(BM) shed on it;
    the earth will conceal its slain no longer.

Footnotes

  1. Isaiah 26:8 Or judgments
  2. Isaiah 26:16 The meaning of the Hebrew for this clause is uncertain.