Add parallel Print Page Options

Àsọtẹ́lẹ̀ kan nípa Jerusalẹmu

22 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó jẹ mọ́ Àfonífojì ìran:

Kí ni ó ń dààmú yín báyìí,
    tí gbogbo yín fi gun orí òrùlé lọ?
Ìwọ ìlú tí ó kún fún rúkèrúdò,
    ìwọ ìlú àìtòrò òun rògbòdìyàn
a kò fi idà pa àwọn òkú rẹ,
    bẹ́ẹ̀ ni wọn kò kú ní ojú ogun.
Gbogbo àwọn olórí i yín ti jùmọ̀ sálọ;
    a ti kó wọn nígbèkùn láìlo ọfà.
Ẹ̀yin tí a mú ni a ti kó lẹ́rú papọ̀,
    lẹ́yìn tí ẹ ti sá nígbà tí ọ̀tá ṣì wà
    lọ́nà jíjìn réré.
Nítorí náà ni mo wí pé, “Yípadà kúrò lọ́dọ̀ mi:
    jẹ́ kí n sọkún kíkorò.
Má ṣe gbìyànjú àti tù mí nínú
    nítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.”

Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kan
    tí rúkèrúdò, rògbòdìyàn àti ẹ̀rùjẹ̀jẹ̀
    ní Àfonífojì ìmọ̀,
ọjọ́ tí a ń wó ògiri lulẹ̀
    àti sísun ẹkún lọ sí àwọn orí òkè.
Elamu mú apó-ọfà lọ́wọ́,
    pẹ̀lú àwọn agun-kẹ̀kẹ́-ogun àti àwọn ẹṣin,
    Kiri yọ àpáta rẹ̀ síta.
Àyànfẹ́ Àfonífojì rẹ kún fún kẹ̀kẹ́ ogun,
    àwọn ẹlẹ́ṣin ni a gbá jọ sí ẹnu-bodè ìlú.

Gbogbo ààbò Juda ni a ti ká kúrò.
Ìwọ sì gbójú sókè ní ọjọ́ náà
    sí àwọn ohun ìjà ní ààfin ti inú aginjù,
Ìwọ rí i pé ìlú u Dafidi
    ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ààyè níbi ààbò rẹ̀,
ìwọ ti tọ́jú omi
    sínú adágún ti ìsàlẹ̀.
10 Ìwọ ka àwọn ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu
    ó sì wó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ilé lulẹ̀ láti fún ògiri lágbára.
11 Ìwọ mọ agbemi sí àárín ògiri méjì
    fún omi inú adágún àtijọ́,
ṣùgbọ́n ìwọ kò wo ẹni tí ó ṣe é tẹ́lẹ̀
    tàbí kí o kọbi ara sí ẹni tí ó
    gbèrò rẹ̀ ní ìgbà pípẹ́ sẹ́yìn.

12 Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
    pè ọ́ ní ọjọ́ náà
láti sọkún kí o sì pohùnréré,
    kí o tu irun rẹ dànù kí o sì
    da aṣọ ọ̀fọ̀ bora.
13 Ṣùgbọ́n Wò ó, ayọ̀ àti ayẹyẹ wà
    màlúù pípa àti àgùntàn pípa,
ẹran jíjẹ àti ọtí wáìnì mímu!
    “Jẹ́ kí a jẹ kí a mu,” ni ẹ̀yin wí,
    “nítorí pé lọ́la àwa ó kú!”

14 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ èyí di mí mọ̀ létí ì mi: “Títí di ọjọ́ ikú yín a kò ní ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ yìí,” ni Olúwa wí, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun.

15 Èyí ni ohun tí Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí:

Lọ, sọ fún ìríjú yìí pé,
    fún Ṣebna, ẹni tí ààfin wà ní ìkáwọ́ rẹ̀:
16 Kí ni ohun tí ò ń ṣe níhìn-ín-yìí àti pé
    ta ni ó sì fún ọ ní àṣẹ
láti gbẹ́ ibojì kan fún ara rẹ níhìn-ín-yìí,
    tí ó gbẹ́ ibojì ní ibi gíga
    tí ó sì gbẹ́ ibi ìsinmi rẹ nínú àpáta?

17 “Kíyèsára, Olúwa fẹ́ gbá ọ mú gírígírí
    kí ó sì jù ọ́ nù, Ìwọ ọkùnrin alágbára.
18 Òun yóò ká ọ rúgúdù bí i òkìtì
    yóò sì sọ ọ́ sí orílẹ̀-èdè ńlá kan.
Níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí
    àti níbẹ̀ pẹ̀lú ni àwọn kẹ̀kẹ́ ogun
àràmọ̀ǹdà rẹ yóò wà—
    ìwọ di ìtìjú sí ilé ọ̀gá rẹ!
19 Èmi yóò yọ ọ́ kúrò ní ipò rẹ,
    a ó sì lé ọ kúrò ní ipò rẹ.

20 “Ní ọjọ́ náà. Èmi yóò ké sí ọmọ ọ̀dọ̀ mi, Eliakimu ọmọ Hilkiah. 21 Èmi yóò fi aṣọ rẹ wọ̀ ọ́, n ó sì so ẹ̀wọ̀n rẹ mọ́ ọn ní ọrùn, èmi ó sì gbé àṣẹ rẹ lé e lọ́wọ́. Òun yó sì jẹ́ baba fún gbogbo olùgbé e Jerusalẹmu àti fún ilé e Juda. 22 (A)Èmi yóò sì fi kọ́kọ́rọ́ ilé e Dafidi lé e ní èjìká; ohunkóhun tí ó bá ṣí, ẹnikẹ́ni kì yóò lè ti, ohunkóhun tí ó bá sì tì, ẹnikẹ́ni kì yóò le è ṣí. 23 Èmi yóò sì kàn mọ́lẹ̀ bí èèkàn tí ó dúró gírígírí ní ààyè e rẹ̀; òun yóò sì jẹ́ ibùjókòó ọlá fún ilé baba rẹ̀. 24 Gbogbo ògo ìdílé rẹ̀ ni wọn yóò sì fi kọ ní ọrùn: ìran rẹ̀ àti àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀, gbogbo ohun èlò ife, títí dé orí ago ọtí.

25 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Èèkàn tí a kàn mọ́lẹ̀ gírígírí ní ààyè e rẹ̀ yóò yẹrí, yóò dẹ̀gbẹ́ yóò sì fẹ̀gbẹ́ lélẹ̀ àti ẹrù tí ó létéńté lórí i rẹ̀ ni a ó gé lulẹ̀.” Olúwa ni ó ti sọ ọ́.

A Prophecy About Jerusalem

22 A prophecy(A) against the Valley(B) of Vision:(C)

What troubles you now,
    that you have all gone up on the roofs,(D)
you town so full of commotion,
    you city of tumult(E) and revelry?(F)
Your slain(G) were not killed by the sword,(H)
    nor did they die in battle.
All your leaders have fled(I) together;
    they have been captured(J) without using the bow.
All you who were caught were taken prisoner together,
    having fled while the enemy was still far away.
Therefore I said, “Turn away from me;
    let me weep(K) bitterly.
Do not try to console me
    over the destruction of my people.”(L)

The Lord, the Lord Almighty, has a day(M)
    of tumult and trampling(N) and terror(O)
    in the Valley of Vision,(P)
a day of battering down walls(Q)
    and of crying out to the mountains.
Elam(R) takes up the quiver,(S)
    with her charioteers and horses;
    Kir(T) uncovers the shield.
Your choicest valleys(U) are full of chariots,
    and horsemen are posted at the city gates.(V)

The Lord stripped away the defenses of Judah,
    and you looked in that day(W)
    to the weapons(X) in the Palace of the Forest.(Y)
You saw that the walls of the City of David
    were broken through(Z) in many places;
you stored up water
    in the Lower Pool.(AA)
10 You counted the buildings in Jerusalem
    and tore down houses(AB) to strengthen the wall.(AC)
11 You built a reservoir between the two walls(AD)
    for the water of the Old Pool,(AE)
but you did not look to the One who made it,
    or have regard(AF) for the One who planned(AG) it long ago.

12 The Lord, the Lord Almighty,
    called you on that day(AH)
to weep(AI) and to wail,
    to tear out your hair(AJ) and put on sackcloth.(AK)
13 But see, there is joy and revelry,(AL)
    slaughtering of cattle and killing of sheep,
    eating of meat and drinking of wine!(AM)
“Let us eat and drink,” you say,
    “for tomorrow we die!”(AN)

14 The Lord Almighty has revealed this in my hearing:(AO) “Till your dying day this sin will not be atoned(AP) for,” says the Lord, the Lord Almighty.

15 This is what the Lord, the Lord Almighty, says:

“Go, say to this steward,
    to Shebna(AQ) the palace(AR) administrator:(AS)
16 What are you doing here and who gave you permission
    to cut out a grave(AT) for yourself(AU) here,
hewing your grave on the height
    and chiseling your resting place in the rock?

17 “Beware, the Lord is about to take firm hold of you
    and hurl(AV) you away, you mighty man.
18 He will roll you up tightly like a ball
    and throw(AW) you into a large country.
There you will die
    and there the chariots(AX) you were so proud of
    will become a disgrace to your master’s house.
19 I will depose you from your office,
    and you will be ousted(AY) from your position.(AZ)

20 “In that day(BA) I will summon my servant,(BB) Eliakim(BC) son of Hilkiah. 21 I will clothe him with your robe and fasten your sash(BD) around him and hand your authority(BE) over to him. He will be a father to those who live in Jerusalem and to the people of Judah. 22 I will place on his shoulder(BF) the key(BG) to the house of David;(BH) what he opens no one can shut, and what he shuts no one can open.(BI) 23 I will drive him like a peg(BJ) into a firm place;(BK) he will become a seat[a] of honor(BL) for the house of his father. 24 All the glory of his family will hang on him: its offspring and offshoots—all its lesser vessels, from the bowls to all the jars.

25 “In that day,(BM)” declares the Lord Almighty, “the peg(BN) driven into the firm place will give way; it will be sheared off and will fall, and the load hanging on it will be cut down.” The Lord has spoken.(BO)

Footnotes

  1. Isaiah 22:23 Or throne