Add parallel Print Page Options

Àsọtẹ́lẹ̀ tó lòdì sí Babeli

21 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan aginjù lẹ́bàá Òkun:

Gẹ́gẹ́ bí ìjì líle ti í jà kọjá ní gúúsù,
    akógunjàlú kan wá láti aginjù,
    láti ilẹ̀ ìpayà.

Ìran tí a ń fojú ṣọ́nà fún ni a ti fihàn mí
    ọlọ̀tẹ̀ ti tu àṣírí, fọ́lé fọ́lé ti kẹ́rù.
Elamu kojú ìjà! Media ti tẹ̀gùn!
    Èmi yóò mú gbogbo Ìpayínkeke dópin,
ni ó búra.

Pẹ̀lú èyí, ìrora mu mi lára gírígírí,
    ìrora gbá mi mú, gẹ́gẹ́ bí i ti
obìnrin tí ń rọbí,
    Mo ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nítorí ohun tí mo gbọ́,
    ọkàn mi pòruurù nípa ohun tí mo rí.
Ọkàn mí dàrú,
    ẹ̀rù mú jìnnìjìnnì bá mi,
ìmọ́lẹ̀ tí mo ti ń fẹ́ ẹ́ rí
    ti wá di ìpayà fún mi.

Wọ́n tẹ́ tábìlì,
    wọ́n tẹ́ ẹní àtẹ́ẹ̀ká,
wọ́n jẹ, wọ́n mu!
    Dìde nílẹ̀, ẹ̀yin ọmọ-aládé,
    ẹ fi òróró kún asà yín!

Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi:

“Lọ, kí o bojúwòde
    kí o sì wá sọ ohun tí ó rí.
Nígbà tí ó bá rí àwọn kẹ̀kẹ́ ogun
    àti àkójọpọ̀ àwọn ẹṣin,
àwọn tó ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́
    tàbí àwọn tí ó gun ìbákasẹ,
jẹ́ kí ó múra sílẹ̀,
    àní ìmúra gidigidi.”

Òun sì kígbe pé, kìnnìún kan;

“Láti ọjọ́ dé ọjọ́, olúwa mi, mo dúró lórí ilé ìṣọ́ ní ọ̀sán,
    a sì fi mí ìṣọ́ mi ní gbogbo òru.
Wò ó, ọkùnrin kan ni ó ń bọ̀ wá yìí
    nínú kẹ̀kẹ́ ogun
àti àkójọpọ̀ àwọn ẹṣin.
    Ó sì mú ìdáhùn padà wá:
‘Babeli ti ṣubú, ó ti ṣubú!
    Gbogbo àwọn ère òrìṣà rẹ̀
    ló fọ́nká sórí ilẹ̀!’ ”

10 Ẹ̀yin ènìyàn mi, tí a gún mọ́lẹ̀ ní ilẹ̀ ìpakà,
    mo sọ ohun tí mo ti gbọ́
láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
    láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Israẹli.

Àsọtẹ́lẹ̀ lòdì sí Edomu

11 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Dumahi:

Ẹnìkan ké sí mi láti Seiri wá
    “Alóre, kí ló kù nínú òru náà?”
12 Alóre náà dáhùn wí pé,
    “Òwúrọ̀ súnmọ́ tòsí, àti òru náà pẹ̀lú.
Bí ìwọ yóò bá béèrè, béèrè
    kí o sì tún padà wá.”

Àsọtẹ́lẹ̀ tó lòdì sí Arabia

13 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Arabia:

Ẹ̀yin ẹgbẹ́ èrò ti Dedani,
    tí ó pàgọ́ sínú igbó Arabia,
14 gbé omi wá fún àwọn tí òǹgbẹ ń gbẹ;
    ẹ̀yin tí ó ń gbé Tema,
    gbé oúnjẹ wá fún àwọn ìsáǹsá.
15 Wọ́n sá kúrò lọ́wọ́ idà,
    kúrò lọ́wọ́ idà tí a fàyọ,
kúrò lọ́wọ́ ọrun tí a fàyọ
    àti kúrò nínú ìgbóná ogun.

16 Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi: “Láàrín ọdún kan, gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀fà tí ó wà lábẹ́ ọgbà, í ti í kà á, gbogbo ògo Kedari yóò wá sí òpin. 17 Àwọn tafàtafà tí ó sálà, àwọn jagunjagun Kedari kò ní tó nǹkan.” Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ni ó ti sọ̀rọ̀.

A Prophecy Against Babylon

21 A prophecy(A) against the Desert(B) by the Sea:

Like whirlwinds(C) sweeping through the southland,(D)
    an invader comes from the desert,
    from a land of terror.

A dire(E) vision has been shown to me:
    The traitor betrays,(F) the looter takes loot.
Elam,(G) attack! Media,(H) lay siege!
    I will bring to an end all the groaning she caused.

At this my body is racked with pain,(I)
    pangs seize me, like those of a woman in labor;(J)
I am staggered by what I hear,
    I am bewildered(K) by what I see.
My heart(L) falters,
    fear makes me tremble;(M)
the twilight I longed for
    has become a horror(N) to me.

They set the tables,
    they spread the rugs,
    they eat, they drink!(O)
Get up, you officers,
    oil the shields!(P)

This is what the Lord says to me:

“Go, post a lookout(Q)
    and have him report what he sees.
When he sees chariots(R)
    with teams of horses,
riders on donkeys
    or riders on camels,(S)
let him be alert,
    fully alert.”

And the lookout[a](T) shouted,

“Day after day, my lord, I stand on the watchtower;
    every night I stay at my post.
Look, here comes a man in a chariot(U)
    with a team of horses.
And he gives back the answer:
    ‘Babylon(V) has fallen,(W) has fallen!
All the images of its gods(X)
    lie shattered(Y) on the ground!’”

10 My people who are crushed on the threshing floor,(Z)
    I tell you what I have heard
from the Lord Almighty,
    from the God of Israel.

A Prophecy Against Edom

11 A prophecy against Dumah[b]:(AA)

Someone calls to me from Seir,(AB)
    “Watchman, what is left of the night?
    Watchman, what is left of the night?”
12 The watchman replies,
    “Morning is coming, but also the night.
If you would ask, then ask;
    and come back yet again.”

A Prophecy Against Arabia

13 A prophecy(AC) against Arabia:(AD)

You caravans of Dedanites,(AE)
    who camp in the thickets of Arabia,
14     bring water for the thirsty;
you who live in Tema,(AF)
    bring food for the fugitives.
15 They flee(AG) from the sword,(AH)
    from the drawn sword,
from the bent bow
    and from the heat of battle.

16 This is what the Lord says to me: “Within one year, as a servant bound by contract(AI) would count it, all the splendor(AJ) of Kedar(AK) will come to an end. 17 The survivors of the archers, the warriors of Kedar, will be few.(AL)” The Lord, the God of Israel, has spoken.(AM)

Footnotes

  1. Isaiah 21:8 Dead Sea Scrolls and Syriac; Masoretic Text A lion
  2. Isaiah 21:11 Dumah, a wordplay on Edom, means silence or stillness.