Add parallel Print Page Options

Òkè Olúwa

Èyí ni ohun tí Isaiah ọmọ Amosi rí nípa Juda àti Jerusalẹmu:

(A)Ní ìgbẹ̀yìn ọjọ́

òkè tẹmpili Olúwa ni a ó fi ìdí rẹ̀ kalẹ̀
    gẹ́gẹ́ bí olú nínú àwọn òkè,
a ó sì gbé e ga ju àwọn òkè kéékèèkéé lọ,
    gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì máa sàn sínú un rẹ̀.

Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni yóò wá, wọn yóò sì wí pé,

“Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á gòkè ńlá Olúwa,
    àti sí ilé Ọlọ́run Jakọbu.
Òun yóò kọ́ wa ní ọ̀nà rẹ̀,
    kí àwa kí ó lè rìn ní ọ̀nà rẹ̀.”
Òfin yóò jáde láti Sioni wá,
    àti ọ̀rọ̀ Olúwa láti Jerusalẹmu.
Òun ó ṣe ìdájọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
    yóò sì parí aáwọ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn.
Wọn yóò fi idà wọn rọ ọkọ́ ìtulẹ̀,
    wọn yóò sì fi ọ̀kọ̀ wọn rọ dòjé.
Orílẹ̀-èdè kì yóò sì gbé idà sí orílẹ̀-èdè mọ́,
    bẹ́ẹ̀ ní wọn kì yóò kọ́ ogun jíjà mọ́.

Wá, ẹ̀yìn ará ilé e Jakọbu,
    ẹ jẹ́ kí a rìn nínú ìmọ́lẹ̀ Olúwa.

Ọjọ́ Olúwa

Ìwọ ti kọ àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀,
    ìwọ ilé Jakọbu.
Wọ́n kún fún ìgbàgbọ́ tí kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀ tí ó ti ìlà-oòrùn wá,
    wọ́n ń wo iṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn Filistini,
    wọ́n ń pa ọwọ́ pọ̀ pẹ̀lú àwọn abọ̀rìṣà.
Ilẹ̀ wọn kún fún fàdákà àti wúrà,
    ìṣúra wọn kò sì ní òpin.
Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ẹṣin,
    kẹ̀kẹ́ ogun wọn kò sì lópin.
Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ère,
    wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún iṣẹ́ ọwọ́ ara wọn,
    èyí tí ìka ọwọ́ àwọn tìkára wọn ti ṣe.
Nítorí náà ni a ó ṣe rẹ ènìyàn sílẹ̀
    ìran ọmọ ènìyàn ni yóò sì di onírẹ̀lẹ̀,
    má ṣe dáríjì wọ́n.

10 Wọ inú àpáta lọ,
    fi ara pamọ́ nínú erùpẹ̀
kúrò nínú ìpayà Olúwa,
    àti ògo ọláńlá rẹ̀!
11 Ojú agbéraga ènìyàn ni a ó rẹ̀ sílẹ̀
    a ó sì tẹrí ìgbéraga ènìyàn ba,
    Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà.

12 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kan ní ìpamọ́
    fún gbogbo agbéraga àti ọlọ́kàn gíga
    nítorí gbogbo àwọn tí a gbéga (ni a ó rẹ̀ sílẹ̀),
13 nítorí gbogbo igi kedari Lebanoni, tó ga tó rìpó
    àti gbogbo óákù Baṣani,
14 nítorí gbogbo òkè gíga ńláńlá
    àti àwọn òkè kéékèèkéé,
15 fún ilé ìṣọ́ gíga gíga
    àti àwọn odi ìdáàbòbò,
16 fún gbogbo ọkọ̀ àwọn oníṣòwò
    àwọn ọkọ̀ tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́.
17 Ìgbéraga ènìyàn ni a ó tẹ̀ lórí ba
    a ó sì rẹ ìgbéraga ènìyàn sílẹ̀,
    Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà,
18 gbogbo ère òrìṣà yóò pòórá.

19 Àwọn ènìyàn yóò sálọ sínú ihò àpáta
    àti sínú ihò ilẹ̀
kúrò lọ́wọ́ ìpayà Olúwa
    àti ògo ọláńlá rẹ̀,
    nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
20 Ní ọjọ́ náà ni àwọn ènìyàn yóò máa sọ
    àwọn ère fàdákà àti ère wúrà
tí wọ́n ti yá fún bíbọ
    sí èkúté àti àwọn àdán,
21 Wọn yóò sálọ sínú ihò ìsàlẹ̀ àpáta
    àti sínú ihò pàlàpálá àpáta
kúrò lọ́wọ́ ìpayà Olúwa
    àti ògo ọláńlá rẹ̀,
    nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.

22 Dẹ́kun à ń gba ènìyàn gbọ́,
    èémí ẹni tó wà ní ihò imú rẹ̀.
Nítorí nínú kín ni a lè kà á sí?

The Mountain of the Lord(A)

This is what Isaiah son of Amoz saw concerning Judah and Jerusalem:(B)

In the last days(C)

the mountain(D) of the Lord’s temple will be established
    as the highest of the mountains;(E)
it will be exalted(F) above the hills,
    and all nations will stream to it.(G)

Many peoples(H) will come and say,

“Come, let us go(I) up to the mountain(J) of the Lord,
    to the temple of the God of Jacob.
He will teach us his ways,
    so that we may walk in his paths.”
The law(K) will go out from Zion,
    the word of the Lord from Jerusalem.(L)
He will judge(M) between the nations
    and will settle disputes(N) for many peoples.
They will beat their swords into plowshares
    and their spears into pruning hooks.(O)
Nation will not take up sword against nation,(P)
    nor will they train for war anymore.

Come, descendants of Jacob,(Q)
    let us walk in the light(R) of the Lord.

The Day of the Lord

You, Lord, have abandoned(S) your people,
    the descendants of Jacob.(T)
They are full of superstitions from the East;
    they practice divination(U) like the Philistines(V)
    and embrace(W) pagan customs.(X)
Their land is full of silver and gold;(Y)
    there is no end to their treasures.(Z)
Their land is full of horses;(AA)
    there is no end to their chariots.(AB)
Their land is full of idols;(AC)
    they bow down(AD) to the work of their hands,(AE)
    to what their fingers(AF) have made.
So people will be brought low(AG)
    and everyone humbled(AH)
    do not forgive them.[a](AI)

10 Go into the rocks, hide(AJ) in the ground
    from the fearful presence of the Lord
    and the splendor of his majesty!(AK)
11 The eyes of the arrogant(AL) will be humbled(AM)
    and human pride(AN) brought low;(AO)
the Lord alone will be exalted(AP) in that day.(AQ)

12 The Lord Almighty has a day(AR) in store
    for all the proud(AS) and lofty,(AT)
for all that is exalted(AU)
    (and they will be humbled),(AV)
13 for all the cedars of Lebanon,(AW) tall and lofty,(AX)
    and all the oaks of Bashan,(AY)
14 for all the towering mountains
    and all the high hills,(AZ)
15 for every lofty tower(BA)
    and every fortified wall,(BB)
16 for every trading ship[b](BC)
    and every stately vessel.
17 The arrogance of man will be brought low(BD)
    and human pride humbled;(BE)
the Lord alone will be exalted in that day,(BF)
18     and the idols(BG) will totally disappear.(BH)

19 People will flee to caves(BI) in the rocks
    and to holes in the ground(BJ)
from the fearful presence(BK) of the Lord
    and the splendor of his majesty,(BL)
    when he rises to shake the earth.(BM)
20 In that day(BN) people will throw away
    to the moles and bats(BO)
their idols of silver and idols of gold,(BP)
    which they made to worship.(BQ)
21 They will flee to caverns in the rocks(BR)
    and to the overhanging crags
from the fearful presence of the Lord
    and the splendor of his majesty,(BS)
    when he rises(BT) to shake the earth.(BU)

22 Stop trusting in mere humans,(BV)
    who have but a breath(BW) in their nostrils.
    Why hold them in esteem?(BX)

Footnotes

  1. Isaiah 2:9 Or not raise them up
  2. Isaiah 2:16 Hebrew every ship of Tarshish