Add parallel Print Page Options

14 Olúwa yóò fi àánú hàn fún Jakọbu,

    yóò tún Israẹli yàn lẹ́ẹ̀kan sí i
    yóò sì fi ìdí wọn kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn tìkára wọn.
Àwọn àjèjì yóò darapọ̀ mọ́ wọn,
    wọn yóò sì fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú ilé e Jakọbu.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbà wọ́n
    wọn yóò sì mú wọn wá sí ààyè e wọn.
Ilé Israẹli yóò gba àwọn orílẹ̀-èdè
    gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin
ní ilẹ̀ Olúwa.
    Wọn yóò kó àwọn akónilẹ́rú wọn ní ìgbèkùn
    wọn yóò sì jẹ ọba lórí àwọn amúnisìn wọn.

Ní ọjọ́ tí Olúwa yóò fi ìtura fún un yín kúrò nínú ìpọ́njú àti ìyà àti ìdè ìkà, ẹ ó sì fi ọ̀rọ̀ àbùkù yìí kan ọba Babeli pé:

    Báwo ni amúnisìn ṣe wá sí òpin!
    Báwo ni ìbínú rẹ̀ ṣe parí!
Olúwa ti dá ọ̀pá ìkà náà,
    ọ̀pá àwọn aláṣẹ,
èyí tí ó ti lu àwọn ènìyàn bolẹ̀
    pẹ̀lú ti kò dáwọ́ dúró,
nínú ìrunú ni ó ṣẹ́gun àwọn orílẹ̀-èdè
    pẹ̀lú ìgbónára tí kò lópin.
Gbogbo ilẹ̀ ni ó wà ní ìsinmi àti àlàáfíà,
    wọ́n bú sí orin.
Pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn igi junifa àti àwọn
    igi kedari ti Lebanoni
ń yọ̀ lórí rẹ wí pé,
    “Níwọ́n bí a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ báyìí,
    kò sí agégi tí yóò wá láti gé wa lulẹ̀.”

Ibojì tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni a ru sókè
    láti pàdé rẹ ní ìpadàbọ̀ rẹ̀
ó ru ẹ̀mí àwọn tí ó ti lọ sókè láti wá kí ọ
    gbogbo àwọn tí ó jẹ́ olórí ní ayé
ó mú kí wọn dìde lórí ìtẹ́ wọn
    gbogbo àwọn tí ó jẹ ọba lórí àwọn orílẹ̀-èdè.
10 Gbogbo wọn yóò dáhùn,
    wọn yóò wí fún ọ wí pé,
“Ìwọ pẹ̀lú ti di aláìlera, gẹ́gẹ́ bí àwa pẹ̀lú
    ìwọ náà ti dàbí wa.”
11 Gbogbo rẹ̀ ni ó di ìrẹ̀sílẹ̀ lọ sí ibojì,
    pẹ̀lú ariwo àwọn dùùrù rẹ,
àwọn ìdin ni wọ́n fọ́nkálẹ̀ lábẹ́ rẹ
    àwọn ekòló sì ti bò ọ́ mọ́lẹ̀.

12 Báwo ni ìwọ ṣe ṣubú lulẹ̀ láti ọ̀run wá,
    ìwọ ìràwọ̀ òwúrọ̀, ọmọ òwúrọ̀ náà!
A ti sọ ọ́ sílẹ̀ sínú ayé
    Ìwọ tí o ti tẹ orí àwọn orílẹ̀-èdè ba rí!
13 Ìwọ sọ nínú ọkàn rẹ pé,
    “Èmi yóò gòkè lọ sí ọ̀run;
Èmi yóò gbé ìtẹ́ mi sókè
    ga ju àwọn ìràwọ̀ Ọlọ́run,
Èmi yóò gúnwà ní orí òkè àpéjọ
    ní ṣóńṣó orí òkè mímọ́.
14 Èmi yóò gòkè lọ rékọjá àwọn àwọsánmọ̀;
    Èmi yóò ṣe ara mi gẹ́gẹ́ bí Ọ̀gá-ògo.”
15 Ṣùgbọ́n a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ wọ inú ibojì lọ
    lọ sí ìsàlẹ̀ ọ̀gbun.

16 Àwọn tí ó rí ọ yóò tẹjúmọ́ ọ,
    wọ́n ronú nípa àtubọ̀tán rẹ:
“Ǹjẹ́ èyí ni ẹni tí ó mi ayé tìtì
    tí ó sì jẹ́ kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì.
17 Ẹni tí ó sọ ayé di aginjù,
    tí ó sì pa ìlú ńláńlá rẹ̀ run
    tí kò dá àwọn òǹdè rẹ̀ sílẹ̀ láti padà sílé?”

18 Gbogbo àwọn ọba orílẹ̀-èdè ni a tẹ́ sílẹ̀
    ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú ibojì tirẹ̀.
19 Ṣùgbọ́n a jù ọ́ síta kúrò nínú ibojì
    gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ka igi tí a kọ̀sílẹ̀,
àwọn tí a pa ni ó bò ọ́ mọ́lẹ̀,
    àwọn tí idà ti gún,
àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú òkúta inú ọ̀gbun.
    Gẹ́gẹ́ bí òkú ó di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ ní abẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀,
20 A kò ní sin ọ́ pẹ̀lú wọn,
    nítorí pé o ti ba ilẹ̀ rẹ jẹ́
    o sì ti pa àwọn ènìyàn rẹ.

Ìran àwọn ìkà
    ni a kì yóò dárúkọ wọn mọ́.
21 Tọ́jú ibìkan tí a ó ti pa àwọn ọmọkùnrin rẹ
    nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn,
    wọn kò gbọdọ̀ dìde láti jogún ilẹ̀
    kí wọ́n sì bo orí ilẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìlú u wọn.

22 “Èmi yóò dìde sókè sí wọn,”
    ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
“Èmi yóò ké orúkọ rẹ̀ kúrò ní Babeli àti àwọn tí ó sálà,
    àwọn ọmọ àti ìran rẹ̀,”
    ni Olúwa wí.
23 Èmi yóò yí i padà sí ibùgbé àwọn òwìwí
    àti sí irà;
Èmi yóò fi ọwọ́ ìparun gbá a,
    ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

Àsọtẹ́lẹ̀ lòdì sí Asiria

24 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra,

    “Gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣètò, bẹ́ẹ̀ ni yóò rí,
    àti bí mo ti pinnu, bẹ́ẹ̀ ni yóò sì dúró.
25 Èmi yóò run Asiria ní ilẹ̀ mi,
    ní àwọn orí òkè mi ni èmi yóò ti rún un mọ́lẹ̀.
    Àjàgà rẹ̀ ni a ó mú kúrò lọ́rùn àwọn ènìyàn mi,
    ẹrù u rẹ̀ ni ó mú kúrò ní èjìká wọn.”

26 Èyí ni ètò tí a pinnu rẹ̀ fún gbogbo ayé,
    èyí ni ọwọ́ tí a nà jáde káàkiri gbogbo orílẹ̀-èdè.
27 Nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti pète,
    ta ni yóò sì ká a lọ́wọ́ kò?
    Ọwọ́ọ rẹ ti nà jáde, ta ni ó sì le è fà á padà?

Àsọtẹ́lẹ̀ lòdì àwọn Filistini

28 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ yí wá ní ọdún tí ọba Ahasi kú:

29 (A)Má ṣe yọ̀, gbogbo ẹ̀yin Filistia,
    pé ọ̀pá tí ó lù ọ́ ti dá;
láti ibi gbòǹgbò ejò náà ni paramọ́lẹ̀
    yóò ti hù jáde,
    èso rẹ̀ yóò sì jẹ́ oró ejò tí í jóni.
30 Ẹni tí ó kúṣẹ̀ẹ́ jù yóò ní pápá oko,
    àwọn aláìní yóò sì dùbúlẹ̀ láìléwu.
Ṣùgbọ́n gbòǹgbò o rẹ̀ ni èmi ó fi ìyàn parun,
    yóò sì ké àwọn ẹni rẹ tí ó sálà kúrò.

31 Hu, ìwọ ẹnu-ọ̀nà! Kígbe, Ìwọ ìlú!
    Yọ́ kúrò, gbogbo ẹ̀yin Filistia!
Èéfín kurukuru kan ti àríwá wá,
    kò sì ṣí amóríbọ́ kan nínú ẹgbẹ́ wọn.
32 Kí ni ìdáhùn tí a ó fún
    agbẹnusọ orílẹ̀-èdè náà?
Olúwa ti fi ìdí Sioni kalẹ̀,
    àti nínú rẹ̀ ni àwọn ènìyàn rẹ̀ tí
    a ti pọ́n ọn lójú yóò ti rí ààbò o wọn.”

14 The Lord will have compassion(A) on Jacob;
    once again he will choose(B) Israel
    and will settle them in their own land.(C)
Foreigners(D) will join them
    and unite with the descendants of Jacob.
Nations will take them
    and bring(E) them to their own place.
And Israel will take possession of the nations(F)
    and make them male and female servants in the Lord’s land.
They will make captives(G) of their captors
    and rule over their oppressors.(H)

On the day the Lord gives you relief(I) from your suffering and turmoil(J) and from the harsh labor forced on you,(K) you will take up this taunt(L) against the king of Babylon:(M)

How the oppressor(N) has come to an end!
    How his fury[a] has ended!
The Lord has broken the rod(O) of the wicked,(P)
    the scepter(Q) of the rulers,
which in anger struck down peoples(R)
    with unceasing blows,
and in fury subdued(S) nations
    with relentless aggression.(T)
All the lands are at rest and at peace;(U)
    they break into singing.(V)
Even the junipers(W) and the cedars of Lebanon
    gloat over you and say,
“Now that you have been laid low,
    no one comes to cut us down.”(X)

The realm of the dead(Y) below is all astir
    to meet you at your coming;
it rouses the spirits of the departed(Z) to greet you—
    all those who were leaders(AA) in the world;
it makes them rise from their thrones—
    all those who were kings over the nations.(AB)
10 They will all respond,
    they will say to you,
“You also have become weak, as we are;
    you have become like us.”(AC)
11 All your pomp has been brought down to the grave,(AD)
    along with the noise of your harps;(AE)
maggots are spread out beneath you
    and worms(AF) cover you.(AG)

12 How you have fallen(AH) from heaven,
    morning star,(AI) son of the dawn!
You have been cast down to the earth,
    you who once laid low the nations!(AJ)
13 You said in your heart,
    “I will ascend(AK) to the heavens;
I will raise my throne(AL)
    above the stars of God;
I will sit enthroned on the mount of assembly,(AM)
    on the utmost heights(AN) of Mount Zaphon.[b]
14 I will ascend above the tops of the clouds;(AO)
    I will make myself like the Most High.”(AP)
15 But you are brought down(AQ) to the realm of the dead,(AR)
    to the depths(AS) of the pit.(AT)

16 Those who see you stare at you,
    they ponder your fate:(AU)
“Is this the man who shook(AV) the earth
    and made kingdoms tremble,
17 the man who made the world a wilderness,(AW)
    who overthrew(AX) its cities
    and would not let his captives go home?”(AY)

18 All the kings of the nations lie in state,
    each in his own tomb.(AZ)
19 But you are cast out(BA) of your tomb
    like a rejected branch;
you are covered with the slain,(BB)
    with those pierced by the sword,(BC)
    those who descend to the stones of the pit.(BD)
Like a corpse trampled underfoot,
20     you will not join them in burial,(BE)
for you have destroyed your land
    and killed your people.

Let the offspring(BF) of the wicked(BG)
    never be mentioned(BH) again.
21 Prepare a place to slaughter his children(BI)
    for the sins of their ancestors;(BJ)
they are not to rise to inherit the land
    and cover the earth with their cities.

22 “I will rise up(BK) against them,”
    declares the Lord Almighty.
“I will wipe out Babylon’s name(BL) and survivors,
    her offspring and descendants,(BM)
declares the Lord.
23 “I will turn her into a place for owls(BN)
    and into swampland;
I will sweep her with the broom of destruction,(BO)
    declares the Lord Almighty.(BP)

24 The Lord Almighty has sworn,(BQ)

“Surely, as I have planned,(BR) so it will be,
    and as I have purposed, so it will happen.(BS)
25 I will crush the Assyrian(BT) in my land;
    on my mountains I will trample him down.
His yoke(BU) will be taken from my people,
    and his burden removed from their shoulders.(BV)

26 This is the plan(BW) determined for the whole world;
    this is the hand(BX) stretched out over all nations.
27 For the Lord Almighty has purposed,(BY) and who can thwart him?
    His hand(BZ) is stretched out, and who can turn it back?(CA)

A Prophecy Against the Philistines

28 This prophecy(CB) came in the year(CC) King Ahaz(CD) died:

29 Do not rejoice, all you Philistines,(CE)
    that the rod that struck you is broken;
from the root of that snake will spring up a viper,(CF)
    its fruit will be a darting, venomous serpent.(CG)
30 The poorest of the poor will find pasture,
    and the needy(CH) will lie down in safety.(CI)
But your root I will destroy by famine;(CJ)
    it will slay(CK) your survivors.(CL)

31 Wail,(CM) you gate!(CN) Howl, you city!
    Melt away, all you Philistines!(CO)
A cloud of smoke comes from the north,(CP)
    and there is not a straggler in its ranks.(CQ)
32 What answer shall be given
    to the envoys(CR) of that nation?
“The Lord has established Zion,(CS)
    and in her his afflicted people will find refuge.(CT)

Footnotes

  1. Isaiah 14:4 Dead Sea Scrolls, Septuagint and Syriac; the meaning of the word in the Masoretic Text is uncertain.
  2. Isaiah 14:13 Or of the north; Zaphon was the most sacred mountain of the Canaanites.