Add parallel Print Page Options

Àsọtẹ́lẹ̀ lòdì sí Babeli

13 (A)Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Babeli

    èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí:
Gbé àsíá sókè ní orí òkè gbẹrẹfu,
    kígbe sí wọn, pè wọ́n
    láti wọlé sí ẹnu-ọ̀nà àwọn ọlọ́lá.
Mo ti pàṣẹ fún àwọn ẹni mímọ́ mi,
    mo ti pe àwọn jagunjagun mi
láti gbé ìbínú mi jáde
    àwọn tí ń yọ̀ nínú ìṣẹ́gun mi.

Gbọ́ ohùn kan ní àwọn orí òkè,
    gẹ́gẹ́ bí i ti ogunlọ́gọ̀ ènìyàn
Gbọ́ ìdàrúdàpọ̀ láàrín àwọn ìjọba,
    gẹ́gẹ́ bí i ti ìkórajọ àwọn orílẹ̀-èdè!
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti kó ogun rẹ̀ jọ
    àwọn jagunjagun fún ogun.
Wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn réré,
    láti ìpẹ̀kun ọ̀run wá
Olúwa pẹ̀lú àwọn ohun ìjà ìbínú rẹ̀,
    láti pa gbogbo orílẹ̀-èdè náà run.

Ẹ hu, nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ tòsí,
    yóò sì wá gẹ́gẹ́ bí ìparun láti ọ̀dọ̀ Alágbára jùlọ.
Nítorí èyí, gbogbo ọwọ́ ni yóò rọ,
    ọkàn ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò rẹ̀wẹ̀sì.
Ẹ̀rù yóò gbá wọn mú,
    ìrora àti ìpayínkeke yóò dìwọ́n mú,
wọn yóò kérora gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó ń rọbí.
    Ẹnìkínní yóò wo ẹnìkejì rẹ̀ pẹ̀lú ìpayà
    ojú wọn á sì gbinájẹ.

Kíyèsi i, ọjọ́ Olúwa ń bọ̀
    ọjọ́ búburú, pẹ̀lú ìbínú
àti ìrunú gbígbóná—
    láti sọ ilẹ̀ náà dahoro,
    àti láti pa àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ inú rẹ̀ run.
10 (B)Àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti ìkójọpọ̀ wọn
    kò sì ní fi ìmọ́lẹ̀ wọn hàn.
Àṣẹ̀ṣẹ̀yọ oòrùn yóò di òkùnkùn
    àti òṣùpá kò ní fi ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ hàn.
11 Èmi yóò jẹ ayé ní ìyà nítorí ibi rẹ̀,
    àwọn ìkà nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Èmi yóò fi òpin sí gààrù àwọn agbéraga
    èmi ó sì rẹ ìgbéraga àwọn aláìláàánú sílẹ̀.
12 Èmi yóò jẹ́ kí ọkùnrin kí ó wọn
    ju ojúlówóo wúrà lọ,
    yóò sì ṣọ̀wọ́n ju wúrà Ofiri lọ.
13 Nítorí náà èmi yóò jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó wárìrì;
    ayé yóò sì mì tìtì ní ibùjókòó rẹ̀
láti ọwọ́ ìbínú Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
    ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ.

14 Gẹ́gẹ́ bí egbin tí à ń dọdẹ rẹ̀,
    gẹ́gẹ́ bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́,
ọ̀kọ̀ọ̀kan yóò padà tọ àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ,
    ọ̀kọ̀ọ̀kan yóò sá padà sí ilẹ̀ abínibí i rẹ̀.
15 Ẹnikẹ́ni tí a bá gbámú ni a ó wọ́ nílẹ̀ tuurutu,
    gbogbo àwọn tí ọwọ́ bá tẹ̀ ni yóò ti ipa idà kú.
16 Àwọn ọ̀dọ́mọdé wọn ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ níṣojú wọn,
    gbogbo ilẹ̀ wọn ni a ó kó
    àwọn aya wọn ni a ó sì bá dàpọ̀.

17 Kíyèsi i, èmi yóò ru àwọn Media sókè sí wọn,
    àwọn tí kò bìkítà fún fàdákà
    tí kò sì ní inú dídùn sí wúrà.
18 Ọrùn wọn yóò ré àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin lulẹ̀;
    wọn kò ní ṣàánú àwọn ọ̀dọ́mọdé
    tàbí kí wọn ṣíjú àánú wo àwọn ọmọdé.
19 Babeli, ohun ọ̀ṣọ́ àwọn ìjọba
    ògo ìgbéraga àwọn ará Babeli
ni Ọlọ́run yóò da ojú rẹ̀ bolẹ̀
    gẹ́gẹ́ bí Sodomu àti Gomorra.
20 A kì yóò tẹ̀ ibẹ̀ dó mọ́
    tàbí kí á gbé inú rẹ̀ láti ìrandíran;
    Ará Arabia kì yóò pa àgọ́ níbẹ̀ mọ́,
    olùṣọ́-àgùntàn kan kì yóò kó ẹran rẹ̀ sinmi níbẹ̀.
21 (C)Ṣùgbọ́n àwọn ẹranko igbó ni yóò dùbúlẹ̀ níbẹ̀,
    àwọn ajáko yóò kún inú ilé wọn,
níbẹ̀ ni àwọn òwìwí yóò máa gbé
    níbẹ̀ ni àwọn ewúrẹ́ igbó yóò ti máa bẹ́ kiri.
22 Ìkookò yóò máa gbó ní ibùba wọn,
    àwọn ajáko nínú arẹwà ààfin wọn.

14 Olúwa yóò fi àánú hàn fún Jakọbu,

    yóò tún Israẹli yàn lẹ́ẹ̀kan sí i
    yóò sì fi ìdí wọn kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn tìkára wọn.
Àwọn àjèjì yóò darapọ̀ mọ́ wọn,
    wọn yóò sì fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú ilé e Jakọbu.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbà wọ́n
    wọn yóò sì mú wọn wá sí ààyè e wọn.
Ilé Israẹli yóò gba àwọn orílẹ̀-èdè
    gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin
ní ilẹ̀ Olúwa.
    Wọn yóò kó àwọn akónilẹ́rú wọn ní ìgbèkùn
    wọn yóò sì jẹ ọba lórí àwọn amúnisìn wọn.

Ní ọjọ́ tí Olúwa yóò fi ìtura fún un yín kúrò nínú ìpọ́njú àti ìyà àti ìdè ìkà, ẹ ó sì fi ọ̀rọ̀ àbùkù yìí kan ọba Babeli pé:

    Báwo ni amúnisìn ṣe wá sí òpin!
    Báwo ni ìbínú rẹ̀ ṣe parí!
Olúwa ti dá ọ̀pá ìkà náà,
    ọ̀pá àwọn aláṣẹ,
èyí tí ó ti lu àwọn ènìyàn bolẹ̀
    pẹ̀lú ti kò dáwọ́ dúró,
nínú ìrunú ni ó ṣẹ́gun àwọn orílẹ̀-èdè
    pẹ̀lú ìgbónára tí kò lópin.
Gbogbo ilẹ̀ ni ó wà ní ìsinmi àti àlàáfíà,
    wọ́n bú sí orin.
Pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn igi junifa àti àwọn
    igi kedari ti Lebanoni
ń yọ̀ lórí rẹ wí pé,
    “Níwọ́n bí a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ báyìí,
    kò sí agégi tí yóò wá láti gé wa lulẹ̀.”

Ibojì tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni a ru sókè
    láti pàdé rẹ ní ìpadàbọ̀ rẹ̀
ó ru ẹ̀mí àwọn tí ó ti lọ sókè láti wá kí ọ
    gbogbo àwọn tí ó jẹ́ olórí ní ayé
ó mú kí wọn dìde lórí ìtẹ́ wọn
    gbogbo àwọn tí ó jẹ ọba lórí àwọn orílẹ̀-èdè.
10 Gbogbo wọn yóò dáhùn,
    wọn yóò wí fún ọ wí pé,
“Ìwọ pẹ̀lú ti di aláìlera, gẹ́gẹ́ bí àwa pẹ̀lú
    ìwọ náà ti dàbí wa.”
11 Gbogbo rẹ̀ ni ó di ìrẹ̀sílẹ̀ lọ sí ibojì,
    pẹ̀lú ariwo àwọn dùùrù rẹ,
àwọn ìdin ni wọ́n fọ́nkálẹ̀ lábẹ́ rẹ
    àwọn ekòló sì ti bò ọ́ mọ́lẹ̀.

12 Báwo ni ìwọ ṣe ṣubú lulẹ̀ láti ọ̀run wá,
    ìwọ ìràwọ̀ òwúrọ̀, ọmọ òwúrọ̀ náà!
A ti sọ ọ́ sílẹ̀ sínú ayé
    Ìwọ tí o ti tẹ orí àwọn orílẹ̀-èdè ba rí!
13 Ìwọ sọ nínú ọkàn rẹ pé,
    “Èmi yóò gòkè lọ sí ọ̀run;
Èmi yóò gbé ìtẹ́ mi sókè
    ga ju àwọn ìràwọ̀ Ọlọ́run,
Èmi yóò gúnwà ní orí òkè àpéjọ
    ní ṣóńṣó orí òkè mímọ́.
14 Èmi yóò gòkè lọ rékọjá àwọn àwọsánmọ̀;
    Èmi yóò ṣe ara mi gẹ́gẹ́ bí Ọ̀gá-ògo.”
15 Ṣùgbọ́n a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ wọ inú ibojì lọ
    lọ sí ìsàlẹ̀ ọ̀gbun.

16 Àwọn tí ó rí ọ yóò tẹjúmọ́ ọ,
    wọ́n ronú nípa àtubọ̀tán rẹ:
“Ǹjẹ́ èyí ni ẹni tí ó mi ayé tìtì
    tí ó sì jẹ́ kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì.
17 Ẹni tí ó sọ ayé di aginjù,
    tí ó sì pa ìlú ńláńlá rẹ̀ run
    tí kò dá àwọn òǹdè rẹ̀ sílẹ̀ láti padà sílé?”

18 Gbogbo àwọn ọba orílẹ̀-èdè ni a tẹ́ sílẹ̀
    ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú ibojì tirẹ̀.
19 Ṣùgbọ́n a jù ọ́ síta kúrò nínú ibojì
    gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ka igi tí a kọ̀sílẹ̀,
àwọn tí a pa ni ó bò ọ́ mọ́lẹ̀,
    àwọn tí idà ti gún,
àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú òkúta inú ọ̀gbun.
    Gẹ́gẹ́ bí òkú ó di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ ní abẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀,
20 A kò ní sin ọ́ pẹ̀lú wọn,
    nítorí pé o ti ba ilẹ̀ rẹ jẹ́
    o sì ti pa àwọn ènìyàn rẹ.

Ìran àwọn ìkà
    ni a kì yóò dárúkọ wọn mọ́.
21 Tọ́jú ibìkan tí a ó ti pa àwọn ọmọkùnrin rẹ
    nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn,
    wọn kò gbọdọ̀ dìde láti jogún ilẹ̀
    kí wọ́n sì bo orí ilẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìlú u wọn.

22 “Èmi yóò dìde sókè sí wọn,”
    ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
“Èmi yóò ké orúkọ rẹ̀ kúrò ní Babeli àti àwọn tí ó sálà,
    àwọn ọmọ àti ìran rẹ̀,”
    ni Olúwa wí.
23 Èmi yóò yí i padà sí ibùgbé àwọn òwìwí
    àti sí irà;
Èmi yóò fi ọwọ́ ìparun gbá a,
    ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

A Prophecy Against Babylon

13 A prophecy(A) against Babylon(B) that Isaiah son of Amoz(C) saw:(D)

Raise a banner(E) on a bare hilltop,
    shout to them;
beckon to them
    to enter the gates(F) of the nobles.
I have commanded those I prepared for battle;
    I have summoned my warriors(G) to carry out my wrath(H)
    those who rejoice(I) in my triumph.

Listen, a noise on the mountains,
    like that of a great multitude!(J)
Listen, an uproar(K) among the kingdoms,
    like nations massing together!
The Lord Almighty(L) is mustering(M)
    an army for war.
They come from faraway lands,
    from the ends of the heavens(N)
the Lord and the weapons(O) of his wrath(P)
    to destroy(Q) the whole country.

Wail,(R) for the day(S) of the Lord is near;
    it will come like destruction(T) from the Almighty.[a](U)
Because of this, all hands will go limp,(V)
    every heart will melt with fear.(W)
Terror(X) will seize them,
    pain and anguish will grip(Y) them;
    they will writhe like a woman in labor.(Z)
They will look aghast at each other,
    their faces aflame.(AA)

See, the day(AB) of the Lord is coming
    —a cruel(AC) day, with wrath(AD) and fierce anger(AE)
to make the land desolate
    and destroy the sinners within it.
10 The stars of heaven and their constellations
    will not show their light.(AF)
The rising sun(AG) will be darkened(AH)
    and the moon will not give its light.(AI)
11 I will punish(AJ) the world for its evil,
    the wicked(AK) for their sins.
I will put an end to the arrogance of the haughty(AL)
    and will humble(AM) the pride of the ruthless.(AN)
12 I will make people(AO) scarcer than pure gold,
    more rare than the gold of Ophir.(AP)
13 Therefore I will make the heavens tremble;(AQ)
    and the earth will shake(AR) from its place
at the wrath(AS) of the Lord Almighty,
    in the day of his burning anger.(AT)

14 Like a hunted(AU) gazelle,
    like sheep without a shepherd,(AV)
they will all return to their own people,
    they will flee(AW) to their native land.(AX)
15 Whoever is captured will be thrust through;
    all who are caught will fall(AY) by the sword.(AZ)
16 Their infants(BA) will be dashed to pieces before their eyes;
    their houses will be looted and their wives violated.(BB)

17 See, I will stir up(BC) against them the Medes,(BD)
    who do not care for silver
    and have no delight in gold.(BE)
18 Their bows(BF) will strike down the young men;(BG)
    they will have no mercy(BH) on infants,
    nor will they look with compassion on children.(BI)
19 Babylon,(BJ) the jewel of kingdoms,(BK)
    the pride and glory(BL) of the Babylonians,[b]
will be overthrown(BM) by God
    like Sodom and Gomorrah.(BN)
20 She will never be inhabited(BO)
    or lived in through all generations;
there no nomads(BP) will pitch their tents,
    there no shepherds will rest their flocks.
21 But desert creatures(BQ) will lie there,
    jackals(BR) will fill her houses;
there the owls(BS) will dwell,
    and there the wild goats(BT) will leap about.
22 Hyenas(BU) will inhabit her strongholds,(BV)
    jackals(BW) her luxurious palaces.
Her time is at hand,(BX)
    and her days will not be prolonged.(BY)

14 The Lord will have compassion(BZ) on Jacob;
    once again he will choose(CA) Israel
    and will settle them in their own land.(CB)
Foreigners(CC) will join them
    and unite with the descendants of Jacob.
Nations will take them
    and bring(CD) them to their own place.
And Israel will take possession of the nations(CE)
    and make them male and female servants in the Lord’s land.
They will make captives(CF) of their captors
    and rule over their oppressors.(CG)

On the day the Lord gives you relief(CH) from your suffering and turmoil(CI) and from the harsh labor forced on you,(CJ) you will take up this taunt(CK) against the king of Babylon:(CL)

How the oppressor(CM) has come to an end!
    How his fury[c] has ended!
The Lord has broken the rod(CN) of the wicked,(CO)
    the scepter(CP) of the rulers,
which in anger struck down peoples(CQ)
    with unceasing blows,
and in fury subdued(CR) nations
    with relentless aggression.(CS)
All the lands are at rest and at peace;(CT)
    they break into singing.(CU)
Even the junipers(CV) and the cedars of Lebanon
    gloat over you and say,
“Now that you have been laid low,
    no one comes to cut us down.”(CW)

The realm of the dead(CX) below is all astir
    to meet you at your coming;
it rouses the spirits of the departed(CY) to greet you—
    all those who were leaders(CZ) in the world;
it makes them rise from their thrones—
    all those who were kings over the nations.(DA)
10 They will all respond,
    they will say to you,
“You also have become weak, as we are;
    you have become like us.”(DB)
11 All your pomp has been brought down to the grave,(DC)
    along with the noise of your harps;(DD)
maggots are spread out beneath you
    and worms(DE) cover you.(DF)

12 How you have fallen(DG) from heaven,
    morning star,(DH) son of the dawn!
You have been cast down to the earth,
    you who once laid low the nations!(DI)
13 You said in your heart,
    “I will ascend(DJ) to the heavens;
I will raise my throne(DK)
    above the stars of God;
I will sit enthroned on the mount of assembly,(DL)
    on the utmost heights(DM) of Mount Zaphon.[d]
14 I will ascend above the tops of the clouds;(DN)
    I will make myself like the Most High.”(DO)
15 But you are brought down(DP) to the realm of the dead,(DQ)
    to the depths(DR) of the pit.(DS)

16 Those who see you stare at you,
    they ponder your fate:(DT)
“Is this the man who shook(DU) the earth
    and made kingdoms tremble,
17 the man who made the world a wilderness,(DV)
    who overthrew(DW) its cities
    and would not let his captives go home?”(DX)

18 All the kings of the nations lie in state,
    each in his own tomb.(DY)
19 But you are cast out(DZ) of your tomb
    like a rejected branch;
you are covered with the slain,(EA)
    with those pierced by the sword,(EB)
    those who descend to the stones of the pit.(EC)
Like a corpse trampled underfoot,
20     you will not join them in burial,(ED)
for you have destroyed your land
    and killed your people.

Let the offspring(EE) of the wicked(EF)
    never be mentioned(EG) again.
21 Prepare a place to slaughter his children(EH)
    for the sins of their ancestors;(EI)
they are not to rise to inherit the land
    and cover the earth with their cities.

22 “I will rise up(EJ) against them,”
    declares the Lord Almighty.
“I will wipe out Babylon’s name(EK) and survivors,
    her offspring and descendants,(EL)
declares the Lord.
23 “I will turn her into a place for owls(EM)
    and into swampland;
I will sweep her with the broom of destruction,(EN)
    declares the Lord Almighty.(EO)

Footnotes

  1. Isaiah 13:6 Hebrew Shaddai
  2. Isaiah 13:19 Or Chaldeans
  3. Isaiah 14:4 Dead Sea Scrolls, Septuagint and Syriac; the meaning of the word in the Masoretic Text is uncertain.
  4. Isaiah 14:13 Or of the north; Zaphon was the most sacred mountain of the Canaanites.

Ìṣubú Babeli

47 (A)“Sọ̀kalẹ̀, jókòó nínú eruku,
    wúńdíá ọmọbìnrin Babeli;
jókòó ní ilẹ̀ láìsí ìtẹ́,
    ọmọbìnrin àwọn ará Babeli.
    A kì yóò pè ọ́ ní aláìlókun àti ẹlẹgẹ́ mọ́.
Mú òkúta-ọlọ kí o sì lọ ìyẹ̀fun;
    mú ìbòjú rẹ kúrò.
Ká aṣọ ẹsẹ̀ rẹ sókè, ká aṣọ itan,
    kí o sì la odò wọ̀n-ọn-nì kọjá.
Ìhòhò rẹ ni a ó sí síta
    àti ìtìjú rẹ ni a ó ṣí sílẹ̀.
Èmi yóò sì gba ẹ̀san;
    Èmi kì yóò sì dá ẹnìkan sí.”

Olùràpadà wa Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀
    òun ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.

“Jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, lọ sínú òkùnkùn,
    ọmọbìnrin àwọn ará Babeli;
a kì yóò pè ọ́ ní ọbabìnrin
    àwọn ilẹ̀ ọba mọ́.
Inú bí mi sí àwọn ènìyàn mi
    tí mo sì ba ogún mi jẹ́;
Mo fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́,
    Ìwọ kò sì ṣíjú àánú wò wọ́n.
Lórí àwọn arúgbó pẹ̀lú
    ní o gbé àjàgà tí ó wúwo lé.
Ìwọ wí pé, ‘Èmi yóò tẹ̀síwájú títí láé—
    ọbabìnrin ayérayé!’
Ṣùgbọ́n ìwọ kò kíyèsi nǹkan wọ̀nyí
    tàbí kí o ronú nípa ohun tí ó lè ṣẹlẹ̀.

(B)“Nísinsin yìí, tẹ́tí sílẹ̀, ìwọ oníwọ̀ra ẹ̀dá
    tí o kẹ̀tẹ̀ǹfẹ̀ nínú ààbò rẹ
tí o sì ń sọ fún ara rẹ pé,
    ‘Èmi ni, kò sì ṣí ẹlòmíràn lẹ́yìn mi.
Èmi kì yóò di opó
    tàbí kí n pàdánù àwọn ọmọ.’
(C)Méjèèjì yìí ni yóò wá sórí rẹ
    láìpẹ́ jọjọ, ní ọjọ́ kan náà:
pípàdánù ọmọ àti dídi opó.
    Wọn yóò wá sórí rẹ ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́,
pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn ìṣe oṣó rẹ
    àti àwọn èpè rẹ tí ko lágbára.
10 Ìwọ ti ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ìwà ìkà rẹ
    ó sì ti wí pé, ‘kò sí ẹni tí ó rí mi?’
Ọgbọ́n àti òye rẹ ti ṣì ọ́ lọ́nà
    nígbà tí o wí fún ara rẹ pé,
    ‘Èmi ni, kò sí ẹlòmíràn lẹ́yìn mi.’
11 Ìparun yóò dé bá ọ
    bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò mọ ọ̀nà láti ré e kúrò.
Àjálù kan yóò ṣubú lù ọ́
    tí o kì yóò le è fi ètùtù ré kúrò;
òfò kan tí o kò le faradà ni
    yóò wá lójijì sí oríì rẹ.

12 “Tẹ̀síwájú nígbà náà, pẹ̀lú àfọ̀ṣẹ rẹ
    àti pẹ̀lú ìwà oṣó rẹ gbogbo,
tí o ti ń ṣiṣẹ́ fún láti ìgbà èwe rẹ wá.
    Bóyá o le è ṣàṣeyọrí,
    bóyá o le è dá rúgúdù sílẹ̀.
13 Gbogbo ìmọ̀ràn tí o ti gbà ni
    ó ti sọ ọ́ di akúrẹtẹ̀!
Jẹ́ kí àwọn awòràwọ̀ rẹ bọ́ síwájú,
    Àwọn awòràwọ̀ tí wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀
láti oṣù dé oṣù,
    jẹ́ kí wọ́n gbà ọ́ lọ́wọ́ ohun tí ó ń bọ̀ wá bá ọ.
14 Lóòótọ́ wọ́n dàbí ìṣẹ́pẹ́ igi;
    iná ni yóò jó wọn dànù.
Wọn kò kúkú lè gba ara wọn là
    lọ́wọ́ agbára iná náà.
Kò sí èédú láti mú ara ẹnikẹ́ni gbóná
    níhìn-ín kò sí iná tí ènìyàn le jókòó tì.
15 Gbogbo ohun tí wọ́n lè ṣe fún ọ nìyìí
    gbogbo èyí ní o tí ṣíṣẹ́ pẹ̀lú u rẹ̀
tí o sì ti ń rù kiri láti ìgbà èwe.
    Ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ń lọ nínú àṣìṣe rẹ̀;
    kò sí ẹyọ ẹnìkan tí ó lè gbà ọ́.

Read full chapter

The Fall of Babylon

47 “Go down, sit in the dust,(A)
    Virgin Daughter(B) Babylon;
sit on the ground without a throne,
    queen city of the Babylonians.[a](C)
No more will you be called
    tender or delicate.(D)
Take millstones(E) and grind(F) flour;
    take off your veil.(G)
Lift up your skirts,(H) bare your legs,
    and wade through the streams.
Your nakedness(I) will be exposed
    and your shame(J) uncovered.
I will take vengeance;(K)
    I will spare no one.(L)

Our Redeemer(M)—the Lord Almighty(N) is his name(O)
    is the Holy One(P) of Israel.

“Sit in silence,(Q) go into darkness,(R)
    queen city of the Babylonians;(S)
no more will you be called
    queen(T) of kingdoms.(U)
I was angry(V) with my people
    and desecrated my inheritance;(W)
I gave them into your hand,(X)
    and you showed them no mercy.(Y)
Even on the aged
    you laid a very heavy yoke.
You said, ‘I am forever(Z)
    the eternal queen!’(AA)
But you did not consider these things
    or reflect(AB) on what might happen.(AC)

“Now then, listen, you lover of pleasure,
    lounging in your security(AD)
and saying to yourself,
    ‘I am, and there is none besides me.(AE)
I will never be a widow(AF)
    or suffer the loss of children.’
Both of these will overtake you
    in a moment,(AG) on a single day:
    loss of children(AH) and widowhood.(AI)
They will come upon you in full measure,
    in spite of your many sorceries(AJ)
    and all your potent spells.(AK)
10 You have trusted(AL) in your wickedness
    and have said, ‘No one sees me.’(AM)
Your wisdom(AN) and knowledge mislead(AO) you
    when you say to yourself,
    ‘I am, and there is none besides me.’
11 Disaster(AP) will come upon you,
    and you will not know how to conjure it away.
A calamity will fall upon you
    that you cannot ward off with a ransom;
a catastrophe you cannot foresee
    will suddenly(AQ) come upon you.

12 “Keep on, then, with your magic spells
    and with your many sorceries,(AR)
    which you have labored at since childhood.
Perhaps you will succeed,
    perhaps you will cause terror.
13 All the counsel you have received has only worn you out!(AS)
    Let your astrologers(AT) come forward,
those stargazers who make predictions month by month,
    let them save(AU) you from what is coming upon you.
14 Surely they are like stubble;(AV)
    the fire(AW) will burn them up.
They cannot even save themselves
    from the power of the flame.(AX)
These are not coals for warmth;
    this is not a fire to sit by.
15 That is all they are to you—
    these you have dealt with
    and labored(AY) with since childhood.
All of them go on in their error;
    there is not one that can save(AZ) you.

Read full chapter

Footnotes

  1. Isaiah 47:1 Or Chaldeans; also in verse 5

Àsọtẹ́lẹ̀ tí wòlíì Habakuku rí.

Ìráhùn Habakuku

(A)Olúwa, èmi yóò ti ké pẹ́ tó fún ìrànlọ́wọ́,
    Ṣùgbọ́n ti ìwọ kò ni fetí sí mi?
Tàbí kígbe sí ọ ní ti, “Ìwà ipá!”
    ṣùgbọ́n tí ìwọ kò sì gbàlà?
Èéṣe tí ìwọ fi mú mi rí àìṣedéédéé
    Èéṣe tí ìwọ sì fi ààyè gba ìwà ìkà?
Ìparun àti ìwà ipá wà ní iwájú mi;
    ìjà ń bẹ, ìkọlù sì wà pẹ̀lú.
Nítorí náà, òfin di ohun àìkàsí,
    ìdájọ́ òdodo kò sì borí.
Àwọn ẹni búburú yí àwọn olódodo ká,
    Nítorí náà ni ìdájọ́ òdodo ṣe yí padà.

Ìdáhùn Olúwa

(B)“Ẹ wo inú àwọn kèfèrí, ki ẹ sí wòye,
    Kí háà kí ó sì ṣe yin gidigidi.
Nítorí èmi ó ṣe ohun kan ní ọjọ́ yín
    tí ẹ̀yin kò jẹ́ gbàgbọ́,
    bí a tilẹ̀ sọ fún yin.
(C)Nítorí pé, èmi yóò gbé àwọn ara Babeli dìde,
    àwọn aláìláàánú àti onínú-fùfù ènìyàn
tí ó rin gbogbo ilẹ̀ ayé já
    láti fi agbára gbà àwọn ibùgbé tí kì í ṣe tiwọn.
Wọn jẹ́ ènìyàn ti a bẹ̀rù, tí a sì páyà,
    ìdájọ́ wọn, àti ọláńlá wọn,
    Yóò máa ti inú wọn jáde.
Ẹṣin wọn yára ju ẹkùn lọ,
    wọ́n sì gbóná jú ìkookò àṣálẹ́ lọ
àwọn ẹlẹ́ṣin wọn yóò sí tan ara wọn ká;
    wọn yóò sì wá láti ọ̀nà jíjìn réré,
wọn yóò sí fò bí ẹyẹ igún tí ń wá láti jẹrun
    Gbogbo wọn sì wà fún ìwà ipá
ìwò ojú wọn yóò sì wá síwájú;
    wọn sì ko ìgbèkùn jọ bí iyanrìn.
10 Wọn ó si máa fi àwọn ọba ṣẹ̀sín
    wọn ó sì tún kẹ́gàn àwọn aládé.
Wọn yóò sì fi gbogbo ìlú odi alágbára nì rẹ́rìn-ín;
    Nítorí pé, wọn yóò ko erùpẹ̀ jọ, wọn yóò sì gbà á
11 Nígbà náà ni inú rẹ̀ yóò yípadà,
    yóò sì rékọjá, yóò si ṣẹ̀ ní kíka agbára rẹ̀ yìí sí iṣẹ́ òrìṣà rẹ̀.”

Ìráhùn lẹ́ẹ̀kejì Habakuku

12 Olúwa, ǹjẹ́ láti ayérayé kọ ni ìwọ tí wà?
    Olúwa Ọlọ́run mi. Ẹni mímọ́ mi, àwa kì yóò kú
Olúwa, ìwọ tí yàn wọn fún ìdájọ́;
    Ọlọ́run alágbára, ìwọ tí fi ẹsẹ̀ wọn múlẹ̀ fún ìbáwí
13 Ojú rẹ mọ́ tónítóní láti wo ibi;
    ìwọ kò le gbà ìwà ìkà
nítorí kí ni ìwọ ṣe gba àwọn alárékérekè láààyè?
    Nítorí kí ni ìwọ ṣe dákẹ́ nígbà tí ẹni búburú ń pa
    ẹni tí i ṣe olódodo ju wọn lọ run?
14 Ìwọ sì tí sọ ènìyàn di bí ẹja inú Òkun,
    bí ohun tí ń rákò tí wọn ko ni alákòóso
15 Àwọn ènìyàn búburú fi àwọ̀n wọn gbé wọn sókè
    ó sì kó wọn jọ nínú àwọ̀n ńlá rẹ̀;
    nítorí náà, ó dunnú, ó sì yọ̀ pẹ̀lú.
16 Nítorí náà, ó rú ẹbọ sí àwọ̀n rẹ̀,
    ó sì ń sun tùràrí fún àwọ̀n ńlá rẹ̀
nítorí pẹ̀lú àwọ̀n rẹ̀ ni ó fi ń gbé ní ìgbádùn
    tí ó sì ń gbádùn pẹ̀lú oúnjẹ tí ó bá wù ú.
17 Ǹjẹ́ wọn yóò ha máa pa àwọ̀n wọn mọ́ ní òfìfo bí,
    tí wọn yóò sì pa orílẹ̀-èdè run láìsí àánú?

Ìdáhùn Ọlọ́run sí ìráhùn wòlíì Habakuku

(D)Èmi yóò dúró lórí ibusọ́ mi láti máa wòye
    Èmi yóò sì gbé ara mi ka orí alóre
Èmi yóò si ṣọ́ láti gbọ́ ohun tí yóò sọ fún mi
    àti èsì ti èmi yóò fún ẹ̀sùn yìí nígbà tó bá ń bá mi wí.

Ìdáhùn Olúwa

Nígbà náà ni Olúwa dáhùn pé:

“Kọ ìṣípayá náà sílẹ̀
    kí o sì fi hàn ketekete lórí wàláà
    kí ẹni tí ń kà á, lè máa sáré.
(E)Nítorí ìṣípayá náà jẹ́ tí ìgbà kan tí a múra sílẹ̀ dè;
    yóò máa yára sí ìgbẹ̀yìn
    kí yóò sìsọ èké.
Bí o tilẹ̀ lọ́ra, dúró dè é;
    nítorí, dájúdájú, yóò dé, kí yóò sí pẹ́.”

(F)“Kíyèsi, ọkàn rẹ tí ó gbéga;
    Ìfẹ́ rẹ̀ kò dúró ṣinṣin nínú rẹ̀,
    ṣùgbọ́n olódodo yóò wa nípa ìgbàgbọ́ rẹ̀.
Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lú, nítorí tí ọtí wáìnì ni ẹ̀tàn,
    agbéraga ènìyàn òun, kò sì ní sinmi
ẹni tí ó sọ ìwọra rẹ di gbígbòòrò bí isà òkú,
    ó sì dàbí ikú, a kò sì le tẹ́ ẹ lọ́rùn,
ó kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ sí ọ̀dọ̀
    ó sì gba gbogbo ènìyàn jọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀.

“Gbogbo àwọn wọ̀nyí kì yóò máa pa òwe sí i tí wọn yóò sì máa kọ orin òwe sí i wí pé,

“ ‘Ègbé ni fún ẹni tí ń mu ohun tí kì í ṣe tirẹ̀ pọ̀ sí i!
    Tí ó sì sọ ara rẹ̀ di ọlọ́rọ̀ nípasẹ̀ ìlọ́nilọ́wọ́gbà!
    Eléyìí yóò ha ti pẹ́ tó?’
Ǹjẹ́ ẹni ti ó yọ ọ́ lẹ́nu, kí yóò ha dìde ní òjijì?
    Àti àwọn tí ó wàhálà rẹ kì yóò jí, kí wọn ó sì dẹ́rùbà ọ́?
    Nígbà náà ni ìwọ yóò wa dí ìkógun fún wọn.
Nítorí ìwọ ti kó orílẹ̀-èdè púpọ̀,
    àwọn ènìyàn tókù yóò sì kó ọ
nítorí ìwọ tí ta ẹ̀jẹ̀ ènìyàn sílẹ̀; nítorí ẹ̀jẹ̀
    Ìwọ tí pa ilẹ̀ àti ìlú ńlá run
    àti gbogbo ènìyàn to ń gbé inú rẹ̀.

“Ègbé ni fún ẹni tí ń jẹ èrè ìjẹkújẹ sí ilé rẹ̀,
    tí o sí gbé ìtẹ́ rẹ̀ lórí ibi gíga,
    kí a ba le gbà á sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ibi!
10 Ìwọ ti gbìmọ̀ ìtìjú sí ilé rẹ
    nípa kíké ènìyàn púpọ̀ kúrò;
    ìwọ sì ti pàdánù ẹ̀mí rẹ
11 Nítorí tí òkúta yóò kígbe jáde láti inú ògiri wá,
    àti ìtí igi láti inú igi rírẹ́ wá yóò sì dá a lóhùn.

12 “Ègbé ni fún ẹni tí ó fi ẹ̀jẹ̀ kọ́ ìlú,
    tí o sì fi àìṣedéédéé tẹ ìlú ńlá dó?
13 Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun kò ha ti ṣètò rẹ̀ pé
    làálàá àwọn ènìyàn jẹ́ epo fún iná
    kí àwọn orílẹ̀-èdè náà sì máa ṣe wàhálà fún asán?
14 Nítorí tí ayé yóò kún fún ìmọ̀ ògo Olúwa,
    bí omi ti bo Òkun.

15 “Ègbé ni fún ẹni tí ó fi ohun mímu fún aládùúgbò rẹ̀,
    tí ó sì fi ọtí-lílé rẹ̀ fún un, tí o sì jẹ́ kó mu àmupara,
    kí ìwọ kí ó ba lè wo ìhòhò wọn”
16 Ìtìjú yóò bò ọ́ dípò ògo, ìwọ náà mu pẹ̀lú
    kí ìhòhò rẹ kí ó lè hàn,
ago ọwọ́ ọ̀tún Olúwa, yóò yípadà sí ọ,
    ìtìjú yóò sì bo ògo rẹ.
17 Nítorí ìwà ipá tí ó tí hù sí Lebanoni yóò bò ọ́,
    àti ìparun àwọn ẹranko yóò dẹ́rùbà ọ́ mọ́lẹ̀
Nítorí ìwọ tí ta ẹ̀jẹ̀ ènìyàn sílẹ̀;
    ìwọ tí pa ilẹ̀ náà àti ìlú ńlá run àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.

18 “Èrè kí ni òrìṣà ni, tí oníṣọ̀nà rẹ̀ fi gbẹ́ ẹ,
    ère dídá ti ń kọ ni èké?
Nítorí ti ẹni ti ó dá a gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé ohun tí ó fúnrarẹ̀ dá;
    ó sì mọ ère tí kò le fọhùn.
19 Ègbé ni fún ẹni ti ń sọ fún igi pé, ‘di alààyè?’
    Fún òkúta tí kò lè fọhùn pé, ‘Dìde’
Ǹjẹ́ òun lè tọ́ ni sí ọ̀nà?
    Wúrà àti fàdákà ni a fi bò ó yíká;
    kò sì sí èémí kan nínú rẹ.”

20 (G)Ṣùgbọ́n Olúwa wà nínú tẹmpili mímọ́ rẹ̀;
    Ẹ jẹ́ kí gbogbo ayé parọ́rọ́ níwájú rẹ.

The prophecy(A) that Habakkuk the prophet received.

Habakkuk’s Complaint

How long,(B) Lord, must I call for help,
    but you do not listen?(C)
Or cry out to you, “Violence!”
    but you do not save?(D)
Why do you make me look at injustice?
    Why do you tolerate(E) wrongdoing?(F)
Destruction and violence(G) are before me;
    there is strife,(H) and conflict abounds.
Therefore the law(I) is paralyzed,
    and justice never prevails.
The wicked hem in the righteous,
    so that justice(J) is perverted.(K)

The Lord’s Answer

“Look at the nations and watch—
    and be utterly amazed.(L)
For I am going to do something in your days
    that you would not believe,
    even if you were told.(M)
I am raising up the Babylonians,[a](N)
    that ruthless and impetuous people,
who sweep across the whole earth(O)
    to seize dwellings not their own.(P)
They are a feared and dreaded people;(Q)
    they are a law to themselves
    and promote their own honor.
Their horses are swifter(R) than leopards,
    fiercer than wolves(S) at dusk.
Their cavalry gallops headlong;
    their horsemen come from afar.
They fly like an eagle swooping to devour;
    they all come intent on violence.
Their hordes[b] advance like a desert wind
    and gather prisoners(T) like sand.
10 They mock kings
    and scoff at rulers.(U)
They laugh at all fortified cities;
    by building earthen ramps(V) they capture them.
11 Then they sweep past like the wind(W) and go on—
    guilty people, whose own strength is their god.”(X)

Habakkuk’s Second Complaint

12 Lord, are you not from everlasting?(Y)
    My God, my Holy One,(Z) you[c] will never die.(AA)
You, Lord, have appointed(AB) them to execute judgment;
    you, my Rock,(AC) have ordained them to punish.
13 Your eyes are too pure(AD) to look on evil;
    you cannot tolerate wrongdoing.(AE)
Why then do you tolerate(AF) the treacherous?(AG)
    Why are you silent while the wicked
    swallow up those more righteous than themselves?(AH)
14 You have made people like the fish in the sea,
    like the sea creatures that have no ruler.
15 The wicked(AI) foe pulls all of them up with hooks,(AJ)
    he catches them in his net,(AK)
he gathers them up in his dragnet;
    and so he rejoices and is glad.
16 Therefore he sacrifices to his net
    and burns incense(AL) to his dragnet,
for by his net he lives in luxury
    and enjoys the choicest food.
17 Is he to keep on emptying his net,
    destroying nations without mercy?(AM)

I will stand at my watch(AN)
    and station myself on the ramparts;(AO)
I will look to see what he will say(AP) to me,
    and what answer I am to give to this complaint.[d](AQ)

The Lord’s Answer

Then the Lord replied:

“Write(AR) down the revelation
    and make it plain on tablets
    so that a herald[e] may run with it.
For the revelation awaits an appointed time;(AS)
    it speaks of the end(AT)
    and will not prove false.
Though it linger, wait(AU) for it;
    it[f] will certainly come
    and will not delay.(AV)

“See, the enemy is puffed up;
    his desires are not upright—
    but the righteous person(AW) will live by his faithfulness[g](AX)
indeed, wine(AY) betrays him;
    he is arrogant(AZ) and never at rest.
Because he is as greedy as the grave
    and like death is never satisfied,(BA)
he gathers to himself all the nations
    and takes captive(BB) all the peoples.

“Will not all of them taunt(BC) him with ridicule and scorn, saying,

“‘Woe to him who piles up stolen goods
    and makes himself wealthy by extortion!(BD)
    How long must this go on?’
Will not your creditors suddenly arise?
    Will they not wake up and make you tremble?
    Then you will become their prey.(BE)
Because you have plundered many nations,
    the peoples who are left will plunder you.(BF)
For you have shed human blood;(BG)
    you have destroyed lands and cities and everyone in them.(BH)

“Woe to him who builds(BI) his house by unjust gain,(BJ)
    setting his nest(BK) on high
    to escape the clutches of ruin!
10 You have plotted the ruin(BL) of many peoples,
    shaming(BM) your own house and forfeiting your life.
11 The stones(BN) of the wall will cry out,
    and the beams of the woodwork will echo it.

12 “Woe to him who builds a city with bloodshed(BO)
    and establishes a town by injustice!
13 Has not the Lord Almighty determined
    that the people’s labor is only fuel for the fire,(BP)
    that the nations exhaust themselves for nothing?(BQ)
14 For the earth will be filled with the knowledge of the glory(BR) of the Lord
    as the waters cover the sea.(BS)

15 “Woe to him who gives drink(BT) to his neighbors,
    pouring it from the wineskin till they are drunk,
    so that he can gaze on their naked bodies!
16 You will be filled with shame(BU) instead of glory.(BV)
    Now it is your turn! Drink(BW) and let your nakedness be exposed[h]!(BX)
The cup(BY) from the Lord’s right hand is coming around to you,
    and disgrace will cover your glory.
17 The violence(BZ) you have done to Lebanon will overwhelm you,
    and your destruction of animals will terrify you.(CA)
For you have shed human blood;(CB)
    you have destroyed lands and cities and everyone in them.

18 “Of what value(CC) is an idol(CD) carved by a craftsman?
    Or an image(CE) that teaches lies?
For the one who makes it trusts in his own creation;
    he makes idols that cannot speak.(CF)
19 Woe to him who says to wood, ‘Come to life!’
    Or to lifeless stone, ‘Wake up!’(CG)
Can it give guidance?
    It is covered with gold and silver;(CH)
    there is no breath in it.”(CI)

20 The Lord is in his holy temple;(CJ)
    let all the earth be silent(CK) before him.

Footnotes

  1. Habakkuk 1:6 Or Chaldeans
  2. Habakkuk 1:9 The meaning of the Hebrew for this word is uncertain.
  3. Habakkuk 1:12 An ancient Hebrew scribal tradition; Masoretic Text we
  4. Habakkuk 2:1 Or and what to answer when I am rebuked
  5. Habakkuk 2:2 Or so that whoever reads it
  6. Habakkuk 2:3 Or Though he linger, wait for him; / he
  7. Habakkuk 2:4 Or faith
  8. Habakkuk 2:16 Masoretic Text; Dead Sea Scrolls, Aquila, Vulgate and Syriac (see also Septuagint) and stagger