Add parallel Print Page Options

Ìdájọ́ fún ẹsẹ̀ Israẹli

Má ṣe yọ̀, ìwọ Israẹli;
    má ṣe hó ìhó ayọ̀ bí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù.
Nítorí ẹ ti jẹ́ aláìṣòótọ́ si Ọlọ́run yín.
    Ẹ fẹ́ràn láti gba owó iṣẹ́ àgbèrè
    ní gbogbo ilẹ̀ ìpakà.
Àwọn ilẹ̀ ìpakà àti ilé ìfun wáìnì kò ní fún àwọn ènìyàn lóúnjẹ
    wáìnì tuntun yóò tàn láìròtẹ́lẹ̀
Wọn kò ní ṣẹ́kù sí ilé Olúwa
    Efraimu yóò padà sí Ejibiti
    Yóò sì jẹ oúnjẹ àìmọ́ ní Asiria.
Wọn kò ní fi ọrẹ ohun mímu fún Olúwa.
    Bẹ́ẹ̀ ni ìrúbọ wọn kò ní mú, inú rẹ̀ dùn.
Ìrú ẹbọ bẹ́ẹ̀ yóò dàbí oúnjẹ àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀.
    Gbogbo àwọn tó bá sì jẹ ẹ́ yóò di aláìmọ́.
Oúnjẹ yìí yóò wà fún wọn fúnrawọn
    kò ní wá sí orí tẹmpili Olúwa.

Kí ni ẹ̀yin ó ṣe ní ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn
    ní àwọn ọjọ́ àjọ̀dún Olúwa?
Bí wọ́n tilẹ̀ yọ́ kúrò lọ́wọ́ ìparun
    Ejibiti yóò kó wọn jọ,
    Memfisi yóò sì sin wọ́n.
Ibi ìsọjọ̀ fàdákà wọn ni ẹ̀gún yóò jogún,
    Ẹ̀gún yóò bo àpótí ìṣúra fàdákà wọn.
Ẹ̀gún yóò sì bo
    gbogbo àgọ́ wọn.
(A)Àwọn ọjọ́ ìjìyà ń bọ̀;
    àwọn ọjọ́ ìṣirò iṣẹ́ ti dé
    Jẹ́ kí Israẹli mọ èyí
Nítorí pé ẹ̀ṣẹ̀ yín pọ̀
    ìkórìíra yín sì pọ̀ gan an ni.
A ka àwọn wòlíì sí òmùgọ̀
    A ka ẹni ìmísí sí asínwín.
Wòlíì, papọ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run,
    ni olùṣọ́ ọ Efraimu.
Síbẹ̀ ìdẹ̀kùn dúró dè é ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀
    àti ìkórìíra ní ilé Ọlọ́run rẹ̀
Wọ́n ti gbilẹ̀ nínú ìwà ìbàjẹ́
    gẹ́gẹ́ bí i ọjọ́ Gibeah
Ọlọ́run yóò rántí ìwà búburú wọn
    yóò sì jẹ wọ́n ní yà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

10 “Mo rí Israẹli bí èso àjàrà ní aginjù.
Mo rí àwọn baba yín,
    bí àkọ́pọ́n nínú igi ọ̀pọ̀tọ́ ní àkọ́so rẹ̀.
Ṣùgbọ́n wọ́n tọ Baali-Peori lọ,
    wọ́n yà wọn sọ́tọ̀ fún òrìṣà tó ń mú ìtìjú bá ni,
ohun ìríra wọn sì rí gẹ́gẹ́ bí wọn ti fẹ́. 11     Ògo Efraimu yóò fò lọ bí ẹyẹ
    kò ní sí ìfẹ́rakù, ìlóyún àti ìbímọ.
12 Bí wọ́n tilẹ̀ tọ́ ọmọ dàgbà.
    Èmi yóò mú wọn ṣọ̀fọ̀ lórí gbogbo wọn
Ègbé ni fún wọn,
    nígbà tí mo yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn!
13 Mo rí Efraimu bí ìlú Tire
    tí a tẹ̀dó sí ibi dáradára
ṣùgbọ́n Efraimu yóò kó àwọn
    ọmọ rẹ̀ jáde fún àwọn apànìyàn.”

14 Fún wọn, Olúwa!
    Kí ni ìwọ yóò fún wọn?
Fún wọn ní inú tí ń ba oyún jẹ́
    àti ọyàn gbígbẹ.

15 “Nítorí gbogbo ìwà búburú tí wọ́n hù ní Gilgali
    Mo kórìíra wọn níbẹ̀,
nítorí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
    Èmi yóò lé wọn jáde ní ilé mi
Èmi kò ní ní ìfẹ́ wọn mọ́
    ọlọ̀tẹ̀ ni gbogbo olórí wọn.
16 Efraimu ti rẹ̀ dànù
    gbogbo rẹ̀ sì ti rọ,
    kò sì so èso,
Bí wọ́n tilẹ̀ bímọ.
    Èmi ó pa àwọn ọmọ wọn tí wọ́n fẹ́ràn jùlọ.”

17 Ọlọ́run mi yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀
    nítorí pé wọn kò gbọ́rọ̀ sí i;
    wọn yóò sì di alárìnkiri láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.

Punishment for Israel

Do not rejoice, Israel;
    do not be jubilant(A) like the other nations.
For you have been unfaithful(B) to your God;
    you love the wages of a prostitute(C)
    at every threshing floor.
Threshing floors and winepresses will not feed the people;
    the new wine(D) will fail them.
They will not remain(E) in the Lord’s land;
    Ephraim will return to Egypt(F)
    and eat unclean food in Assyria.(G)
They will not pour out wine offerings(H) to the Lord,
    nor will their sacrifices please(I) him.
Such sacrifices will be to them like the bread of mourners;(J)
    all who eat them will be unclean.(K)
This food will be for themselves;
    it will not come into the temple of the Lord.(L)

What will you do(M) on the day of your appointed festivals,(N)
    on the feast days of the Lord?
Even if they escape from destruction,
    Egypt will gather them,(O)
    and Memphis(P) will bury them.(Q)
Their treasures of silver(R) will be taken over by briers,
    and thorns(S) will overrun their tents.
The days of punishment(T) are coming,
    the days of reckoning(U) are at hand.
    Let Israel know this.
Because your sins(V) are so many
    and your hostility so great,
the prophet is considered a fool,(W)
    the inspired person a maniac.(X)
The prophet, along with my God,
    is the watchman over Ephraim,[a]
yet snares(Y) await him on all his paths,
    and hostility in the house of his God.(Z)
They have sunk deep into corruption,(AA)
    as in the days of Gibeah.(AB)
God will remember(AC) their wickedness
    and punish them for their sins.(AD)

10 “When I found Israel,
    it was like finding grapes in the desert;
when I saw your ancestors,
    it was like seeing the early fruit(AE) on the fig(AF) tree.
But when they came to Baal Peor,(AG)
    they consecrated themselves to that shameful idol(AH)
    and became as vile as the thing they loved.
11 Ephraim’s glory(AI) will fly away like a bird(AJ)
    no birth, no pregnancy, no conception.(AK)
12 Even if they rear children,
    I will bereave(AL) them of every one.
Woe(AM) to them
    when I turn away from them!(AN)
13 I have seen Ephraim,(AO) like Tyre,
    planted in a pleasant place.(AP)
But Ephraim will bring out
    their children to the slayer.”(AQ)

14 Give them, Lord
    what will you give them?
Give them wombs that miscarry
    and breasts that are dry.(AR)

15 “Because of all their wickedness in Gilgal,(AS)
    I hated them there.
Because of their sinful deeds,(AT)
    I will drive them out of my house.
I will no longer love them;(AU)
    all their leaders are rebellious.(AV)
16 Ephraim(AW) is blighted,
    their root is withered,
    they yield no fruit.(AX)
Even if they bear children,
    I will slay(AY) their cherished offspring.”

17 My God will reject(AZ) them
    because they have not obeyed(BA) him;
    they will be wanderers among the nations.(BB)

Footnotes

  1. Hosea 9:8 Or The prophet is the watchman over Ephraim, / the people of my God