Add parallel Print Page Options

Ẹ̀sùn tí Ọlọ́run fi kan Israẹli

Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọmọ Israẹli,
    nítorí pé Olúwa fi ẹ̀sùn
    kan ẹ̀yin tí ń gbé ní ilẹ̀ náà.
“Kò sí ìwà òtítọ́, kò sí ìfẹ́
    Kò sí ìmọ̀ Ọlọ́run ní ilẹ̀ náà
Àfi èpè, irọ́ pípa àti ìpànìyàn
    olè jíjà àti panṣágà.
Wọ́n rú gbogbo òfin,
    ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sì ń gorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀.
Nítorí èyí, ilẹ̀ náà ń ṣọ̀fọ̀, gbogbo
    olùgbé ibẹ̀ sì ń ṣòfò dànù.
Ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run
    àti ẹja inú omi ló ń kú.

“Ṣùgbọ́n kí ẹnikẹ́ni má ṣe mú ẹ̀sùn wá,
    kí ẹnìkan má sì ṣe fi ẹ̀sùn kan ẹnìkejì
nítorí àwọn ènìyàn rẹ̀ dàbí
    àwọn ti ń fi ẹ̀sùn kan àlùfáà
Ẹ ń ṣubú lọ́sàn án àti lóru
    àwọn wòlíì yín sì ń ṣubú pẹ̀lú yín
Èmi ó pa ìyá rẹ run
    Àwọn ènìyàn mi ń ṣègbé nítorí pé wọn kò ní ìmọ̀.

“Nítorí pé ẹ ti kọ ìmọ̀ sílẹ̀.
    Èmi náà kọ̀ yín ní àlùfáà mi;
nítorí pé ẹ ti kọ òfin Ọlọ́run yín sílẹ̀
    Èmi náà yóò gbàgbé àwọn ọmọ yín.
Bí àwọn àlùfáà ṣe ń pọ̀ sí i
    bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń dẹ́ṣẹ̀ sí mi.
    Wọ́n yí ògo mi padà sí ohun ìtìjú
wọ́n ń jẹun nípa ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi
    Wọ́n sì ń gbádùn nínú ìwà búburú wọn.
Yóò sì ṣe gẹ́gẹ́: bí ènìyàn ṣe rí náà ni àwọn àlùfáà rí
    Èmi ó jẹ gbogbo wọn ní yà nítorí ọ̀nà wọn.
    Èmi ó sì san án fún wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn.

10 “Wọn ó máa jẹun ṣùgbọ́n wọn kò ní yó;
    wọn ó ṣe àgbèrè ṣùgbọ́n, wọn kò ni pọ̀ sí i,
nítorí pé wọ́n ti kọ Olúwa
sílẹ̀ 11     ‘Wọ́n sì ti fi ara wọn’ fún àgbèrè,
wọ́n fi ara wọn fún wáìnì àtijọ́
àti tuntun èyí tó gba òye àwọn ènìyàn mi sọnù 12     Wọ́n ń gba ìmọ̀ràn lọ́wọ́ ère igi
ọ̀pá igi sì ń dá wọn lóhùn.
    Ẹ̀mí àgbèrè ti mú wọn ṣìnà
    wọ́n sì jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wọn.
13 Wọ́n ń rú ẹbọ lórí àwọn òkè ńlá,
    Wọ́n sì ń sun ọrẹ tùràrí lórí àwọn òkè kékeré
Lábẹ́ igi óákù, àti igi Poplari
    àti igi ẹlimuati onírúurú igi tí ìbòjú rẹ̀ dára
Nítorí náà àwọn ọmọbìnrin yín yóò ṣe àgbèrè
    àti àwọn àfẹ́sọ́nà yín yóò ṣe àgbèrè.

14 “Èmi kò ní jẹ àwọn ọmọbìnrin yín
    ní yà nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè
tàbí àwọn àfẹ́sọ́nà ọmọ yín,
    nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè
nítorí pé àwọn ọkùnrin pàápàá ń bá alágbèrè kẹ́gbẹ́.
    Wọ́n sì ń rú ẹbọ pẹ̀lú àwọn alágbèrè ojúbọ òrìṣà.
    Nítorí náà, ènìyàn tí kò bá ní òye yóò parun!

15 “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o ṣe àgbèrè ìwọ Israẹli
    Ìdájọ́ yìí wà fún un yín Ẹ má ṣe jẹ́ kí Juda di ẹlẹ́bi.

“Ẹ má ṣe lọ sí Gilgali.
    Ẹ má sì ṣe gòkè lọ sí Beti-Afeni
    ẹ má sì búra pé, ‘Bí Olúwa ti wà láààyè nítòótọ́!’
16 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe agídí
    bí alágídí ọmọ màlúù
Báwo wá ni Olúwa ṣe fẹ́ bọ́ wọn
    bí àgùntàn ní pápá oko tútù?
17 Efraimu ti darapọ̀ mọ́
    òrìṣà Ẹ fi sílẹ̀!
18 Bí ohun mímu wọn bá tilẹ̀ tán
    wọ́n tún tẹ̀síwájú nínú àgbèrè
    Àwọn olórí wọn fẹ́ràn ohun ìtìjú ju ohun ìyìn lọ.
19 Ìjì ni yóò gbá wọn lọ.
    Gbogbo ìrúbọ wọn yóò sì kó ìtìjú bá wọn.

The Charge Against Israel

Hear the word of the Lord, you Israelites,
    because the Lord has a charge(A) to bring
    against you who live in the land:(B)
“There is no faithfulness,(C) no love,
    no acknowledgment(D) of God in the land.(E)
There is only cursing,[a] lying(F) and murder,(G)
    stealing(H) and adultery;(I)
they break all bounds,
    and bloodshed follows bloodshed.(J)
Because of this the land dries up,(K)
    and all who live in it waste away;(L)
the beasts of the field, the birds in the sky
    and the fish in the sea are swept away.(M)

“But let no one bring a charge,
    let no one accuse another,
for your people are like those
    who bring charges against a priest.(N)
You stumble(O) day and night,
    and the prophets stumble with you.
So I will destroy your mother(P)
    my people are destroyed from lack of knowledge.(Q)

“Because you have rejected knowledge,
    I also reject you as my priests;
because you have ignored the law(R) of your God,
    I also will ignore your children.
The more priests there were,
    the more they sinned against me;
    they exchanged their glorious God[b](S) for something disgraceful.(T)
They feed on the sins of my people
    and relish their wickedness.(U)
And it will be: Like people, like priests.(V)
    I will punish both of them for their ways
    and repay them for their deeds.(W)

10 “They will eat but not have enough;(X)
    they will engage in prostitution(Y) but not flourish,
because they have deserted(Z) the Lord
    to give themselves 11 to prostitution;(AA)
old wine(AB) and new wine
    take away their understanding.(AC)
12 My people consult a wooden idol,(AD)
    and a diviner’s rod speaks to them.(AE)
A spirit of prostitution(AF) leads them astray;(AG)
    they are unfaithful(AH) to their God.
13 They sacrifice on the mountaintops
    and burn offerings on the hills,
under oak,(AI) poplar and terebinth,
    where the shade is pleasant.(AJ)
Therefore your daughters turn to prostitution(AK)
    and your daughters-in-law to adultery.(AL)

14 “I will not punish your daughters
    when they turn to prostitution,
nor your daughters-in-law
    when they commit adultery,
because the men themselves consort with harlots(AM)
    and sacrifice with shrine prostitutes(AN)
    a people without understanding(AO) will come to ruin!(AP)

15 “Though you, Israel, commit adultery,
    do not let Judah become guilty.

“Do not go to Gilgal;(AQ)
    do not go up to Beth Aven.[c](AR)
    And do not swear, ‘As surely as the Lord lives!’(AS)
16 The Israelites are stubborn,(AT)
    like a stubborn heifer.(AU)
How then can the Lord pasture them
    like lambs(AV) in a meadow?
17 Ephraim is joined to idols;
    leave him alone!
18 Even when their drinks are gone,
    they continue their prostitution;
    their rulers dearly love shameful ways.
19 A whirlwind(AW) will sweep them away,
    and their sacrifices will bring them shame.(AX)

Footnotes

  1. Hosea 4:2 That is, to pronounce a curse on
  2. Hosea 4:7 Syriac (see also an ancient Hebrew scribal tradition); Masoretic Text me; / I will exchange their glory
  3. Hosea 4:15 Beth Aven means house of wickedness (a derogatory name for Bethel, which means house of God).