Add parallel Print Page Options

Jakọbu lọ sí Ejibiti

46 Báyìí ni Israẹli mú ìrìnàjò rẹ̀ pọ̀n pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ní, nígbà tí ó sì dé Beerṣeba, ó rú ẹbọ sí Ọlọ́run Isaaki baba rẹ̀.

Ọlọ́run sì bá Israẹli sọ̀rọ̀ ní ojú ìran ní òru pé, “Jakọbu! Jakọbu!”

Ó sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”

Ọlọ́run sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run, Ọlọ́run baba rẹ, má ṣe bẹ̀rù láti sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti nítorí, èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá níbẹ̀. Èmi yóò sì sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ lọ sí Ejibiti, èmi yóò sì tún mú ọ padà wá. Ọwọ́ Josẹfu fúnrarẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí.”

Nígbà náà ni Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, àwọn ọmọ Israẹli sì mú Jakọbu baba wọn àti àwọn aya wọn àti àwọn ọmọ wọn, wọ́n sì kó wọn sí inú kẹ̀kẹ́ ẹrù tí Farao fi ránṣẹ́ fún ìrìnàjò rẹ̀: (A)Wọ́n tún kó àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti ní láti ilẹ̀ Kenaani, Jakọbu àti gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti. Ó kó àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ obìnrin, gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ lọ sí Ejibiti.

(B)Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ Israẹli (Jakọbu àti Ìran rẹ̀) tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ Ejibiti:

Reubeni àkọ́bí Jakọbu.

Àwọn ọmọkùnrin Reubeni:

Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi.

10 Àwọn ọmọkùnrin Simeoni:

Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu, tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọbìnrin ará Kenaani.

11 Àwọn ọmọkùnrin Lefi:

Gerṣoni, Kohati àti Merari.

12 Àwọn ọmọkùnrin Juda:

Eri, Onani, Ṣela, Peresi àti Sera (ṣùgbọ́n Ẹri àti Onani ti kú ní ilẹ̀ Kenaani).

Àwọn ọmọ Peresi:

Hesroni àti Hamulu.

13 Àwọn ọmọkùnrin Isakari!

Tola, Pua, Jaṣibu àti Ṣimroni.

14 Àwọn ọmọkùnrin Sebuluni:

Seredi, Eloni àti Jahaleli.

15 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin Lea tí ó bí fún Jakọbu ní Padani-Aramu yàtọ̀ fún Dina ọmọbìnrin rẹ̀. Àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọ̀nyí jẹ́ mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lápapọ̀.

16 Àwọn ọmọkùnrin Gadi:

Sefoni, Haggi, Ṣuni, Esboni, Eri, Arodi, àti Areli.

17 Àwọn ọmọkùnrin Aṣeri:

Imina, Iṣifa, Iṣfi àti Beriah. Arábìnrin wọn ni Sera.

Àwọn ọmọkùnrin Beriah:

Heberi àti Malkieli.

18 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Jakọbu bí nípasẹ̀ Silipa, ẹni tí Labani fi fún Lea ọmọbìnrin rẹ̀. Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́rìn-dínlógún (16) lápapọ̀.

19 Àwọn ọmọkùnrin Rakeli aya Jakọbu:

Josẹfu àti Benjamini.

20 Ní Ejibiti, Asenati ọmọbìnrin Potifẹra, alábojútó àti àlùfáà Oni, bí Manase àti Efraimu fún Josẹfu.

21 Àwọn ọmọ Benjamini:

Bela, Bekeri, Aṣbeli, Gera, Naamani, Ehi, Roṣi, Mupimu, Huppimu àti Ardi.

22 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Rakeli bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ mẹ́rìnlá (14) lápapọ̀.

23 Àwọn ọmọ Dani:

Huṣimu.

24 Àwọn ọmọ Naftali:

Jasieli, Guni, Jeseri, àti Ṣillemu.

25 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Biliha ẹni tí Labani fi fún Rakeli ọmọ rẹ̀ bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ méje lápapọ̀.

26 Gbogbo àwọn tí ó lọ pẹ̀lú Jakọbu sí Ejibiti, àwọn tí ó jẹ́ ìran rẹ̀ tààrà láìka àwọn aya ọmọ rẹ̀, jẹ́ ènìyàn mẹ́rìn-dín-ní-àádọ́rin (66). 27 (C)Pẹ̀lú àwọn ọmọkùnrin méjì tí a bí fún Josẹfu ní Ejibiti àwọn ará ilé Jakọbu tí ó lọ sí Ejibiti jẹ́ àádọ́rin (70) lápapọ̀.

28 Jakọbu sì rán Juda ṣáájú rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Josẹfu, kí wọn bá à le mọ ọ̀nà Goṣeni. Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Goṣeni, 29 Josẹfu tọ́jú kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì lọ sí Goṣeni láti pàdé Israẹli baba rẹ̀. Bí Josẹfu ti dé iwájú baba rẹ̀, ó dì mọ́ baba rẹ̀ ó sì sọkún fún ìgbà pípẹ́.

30 Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Wàyí o, mo le kú, níwọ̀n bí mo ti rí i fún ara mi pé, o wà láààyè síbẹ̀.”

31 Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ àti fún àwọn ará ilé baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò gòkè lọ, èmi yóò sì bá Farao sọ̀rọ̀, èmi yóò sì wí fún un pé, Àwọn arákùnrin mi àti ìdílé baba mi tí ń gbé ní Kenaani ti tọ̀ mí wá. 32 Darandaran ni àwọn ènìyàn náà, wọ́n ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn, wọ́n sì kó agbo ẹran wọn àti agbo màlúù wọn àti gbogbo ohun tí wọ́n ní pẹ̀lú wá.” 33 Nígbà tí Farao bá pè yín wọlé tí ó sí béèrè irú iṣẹ́ tí ẹ ń ṣe, 34 ẹ fún un lésì pé, “àwọn ìránṣẹ́ rẹ ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn ni láti ìgbà èwe wa wá gẹ́gẹ́ bí a ṣe ba a lọ́wọ́ àwọn baba wa.” Nígbà náà ni wọn yóò fún un yín láààyè láti tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni. Nítorí pé àwọn ará Ejibiti kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ darandaran.

Jacob Goes to Egypt

46 So Israel(A) set out with all that was his, and when he reached Beersheba,(B) he offered sacrifices(C) to the God of his father Isaac.(D)

And God spoke to Israel(E) in a vision at night(F) and said, “Jacob! Jacob!”

“Here I am,”(G) he replied.

“I am God, the God of your father,”(H) he said. “Do not be afraid(I) to go down to Egypt,(J) for I will make you into a great nation(K) there.(L) I will go down to Egypt with you, and I will surely bring you back again.(M) And Joseph’s own hand will close your eyes.(N)

Then Jacob left Beersheba,(O) and Israel’s(P) sons took their father Jacob and their children and their wives in the carts(Q) that Pharaoh had sent to transport him. So Jacob and all his offspring went to Egypt,(R) taking with them their livestock and the possessions(S) they had acquired(T) in Canaan. Jacob brought with him to Egypt(U) his sons and grandsons and his daughters and granddaughters—all his offspring.(V)

These are the names of the sons of Israel(W) (Jacob and his descendants) who went to Egypt:

Reuben the firstborn(X) of Jacob.

The sons of Reuben:(Y)

Hanok, Pallu,(Z) Hezron and Karmi.(AA)

10 The sons of Simeon:(AB)

Jemuel,(AC) Jamin, Ohad, Jakin, Zohar(AD) and Shaul the son of a Canaanite woman.

11 The sons of Levi:(AE)

Gershon,(AF) Kohath(AG) and Merari.(AH)

12 The sons of Judah:(AI)

Er,(AJ) Onan,(AK) Shelah, Perez(AL) and Zerah(AM) (but Er and Onan had died in the land of Canaan).(AN)

The sons of Perez:(AO)

Hezron and Hamul.(AP)

13 The sons of Issachar:(AQ)

Tola, Puah,[a](AR) Jashub[b](AS) and Shimron.

14 The sons of Zebulun:(AT)

Sered, Elon and Jahleel.

15 These were the sons Leah bore to Jacob in Paddan Aram,[c](AU) besides his daughter Dinah.(AV) These sons and daughters of his were thirty-three in all.

16 The sons of Gad:(AW)

Zephon,[d](AX) Haggi, Shuni, Ezbon, Eri, Arodi and Areli.

17 The sons of Asher:(AY)

Imnah, Ishvah, Ishvi and Beriah.

Their sister was Serah.

The sons of Beriah:

Heber and Malkiel.

18 These were the children born to Jacob by Zilpah,(AZ) whom Laban had given to his daughter Leah(BA)—sixteen in all.

19 The sons of Jacob’s wife Rachel:(BB)

Joseph and Benjamin.(BC) 20 In Egypt, Manasseh(BD) and Ephraim(BE) were born to Joseph(BF) by Asenath daughter of Potiphera, priest of On.[e](BG)

21 The sons of Benjamin:(BH)

Bela, Beker, Ashbel, Gera, Naaman, Ehi, Rosh, Muppim, Huppim and Ard.(BI)

22 These were the sons of Rachel(BJ) who were born to Jacob—fourteen in all.

23 The son of Dan:(BK)

Hushim.(BL)

24 The sons of Naphtali:(BM)

Jahziel, Guni, Jezer and Shillem.

25 These were the sons born to Jacob by Bilhah,(BN) whom Laban had given to his daughter Rachel(BO)—seven in all.

26 All those who went to Egypt with Jacob—those who were his direct descendants, not counting his sons’ wives—numbered sixty-six persons.(BP) 27 With the two sons[f] who had been born to Joseph in Egypt,(BQ) the members of Jacob’s family, which went to Egypt, were seventy[g] in all.(BR)

28 Now Jacob sent Judah(BS) ahead of him to Joseph to get directions to Goshen.(BT) When they arrived in the region of Goshen, 29 Joseph had his chariot(BU) made ready and went to Goshen to meet his father Israel.(BV) As soon as Joseph appeared before him, he threw his arms around his father[h] and wept(BW) for a long time.(BX)

30 Israel(BY) said to Joseph, “Now I am ready to die, since I have seen for myself that you are still alive.”(BZ)

31 Then Joseph said to his brothers and to his father’s household, “I will go up and speak to Pharaoh and will say to him, ‘My brothers and my father’s household, who were living in the land of Canaan,(CA) have come to me.(CB) 32 The men are shepherds;(CC) they tend livestock,(CD) and they have brought along their flocks and herds and everything they own.’(CE) 33 When Pharaoh calls you in and asks, ‘What is your occupation?’(CF) 34 you should answer, ‘Your servants(CG) have tended livestock from our boyhood on, just as our fathers did.’(CH) Then you will be allowed to settle(CI) in the region of Goshen,(CJ) for all shepherds are detestable to the Egyptians.(CK)

Footnotes

  1. Genesis 46:13 Samaritan Pentateuch and Syriac (see also 1 Chron. 7:1); Masoretic Text Puvah
  2. Genesis 46:13 Samaritan Pentateuch and some Septuagint manuscripts (see also Num. 26:24 and 1 Chron. 7:1); Masoretic Text Iob
  3. Genesis 46:15 That is, Northwest Mesopotamia
  4. Genesis 46:16 Samaritan Pentateuch and Septuagint (see also Num. 26:15); Masoretic Text Ziphion
  5. Genesis 46:20 That is, Heliopolis
  6. Genesis 46:27 Hebrew; Septuagint the nine children
  7. Genesis 46:27 Hebrew (see also Exodus 1:5 and note); Septuagint (see also Acts 7:14) seventy-five
  8. Genesis 46:29 Hebrew around him