Add parallel Print Page Options

Àwọn ìlànà ọjọ́ ìsinmi

35 Mose pe gbogbo ìjọ Israẹli ó sì wí fún wọn pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ohun ti Olúwa ti pàṣẹ fún un yín láti ṣe: (A)Fún ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje yóò jẹ́ ọjọ́ mímọ́ fún yín, ọjọ́ ìsinmi ni sí Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ni ọjọ́ náà ní a ó pa. Ẹ má ṣe dáná kankan ní ibùgbé yín ní ọjọ́ ìsinmi.”

Ohun èlò fun Àgọ́

(B)Mose sọ fún gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ: Láti inú ohun tí ẹ ni ni kí ẹ ti mú ọrẹ fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ ni kí ó mú ọrẹ fún Olúwa ní ti:

“wúrà, fàdákà àti idẹ;

aṣọ aláró, elése àlùkò, òdòdó àti ọ̀gbọ̀ dáradára;

àti irun ewúrẹ́;

awọ àgbò tí a kùn ní pupa àti awọ màlúù;

odò igi kasia;

òróró olifi fún títan iná;

olóòórùn fún òróró ìtasórí, àti fún tùràrí dídùn;

òkúta óníkìsì àti òkúta tí a tò sí ẹ̀wù efodu àti ìgbàyà.

10 “Gbogbo ẹni tí ó ní ọgbọ́n láàrín yín, kí ó wa, kí ó sì wá ṣe gbogbo ohun tí Olúwa ti pàṣẹ:

11 “àgọ́ náà pẹ̀lú àgọ́ rẹ àti ìbòrí rẹ̀, kọ́kọ́rọ́ rẹ̀, pákó rẹ̀, ọ̀pá rẹ̀, ọ̀wọ́n rẹ̀ àti ihò ìtẹ̀bọ̀ rẹ̀;

12 Àpótí náà pẹ̀lú ọ̀pá rẹ̀, ìbò àánú àti aṣọ títa náà tí ó ṣíji bò ó;

13 Tábìlì náà pẹ̀lú òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀ àti àkàrà ìfihàn náà;

14 Ọ̀pá fìtílà tí ó wà fún títanná pẹ̀lú ohun èlò rẹ̀, fìtílà àti òróró fún títanná;

15 Pẹpẹ tùràrí náà pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀, òróró ìtasórí àti tùràrí dídùn;

aṣọ títa fún ọ̀nà ìlẹ̀kùn ní ẹnu-ọ̀nà sí àgọ́ náà;

16 Pẹpẹ ẹbọ sísun pẹ̀lú ojú ààrò idẹ rẹ̀, òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀;

agbada idẹ pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀;

17 aṣọ títa ti àgbàlá pẹ̀lú, ọ̀wọ́n àti ihò ìtẹ̀bọ̀ rẹ̀ àti aṣọ títa fún ẹnu-ọ̀nà àgbàlá náà;

18 Èèkàn àgọ́ náà fún àgọ́ náà àti fún àgbàlá àti okùn wọn;

19 aṣọ híhun láti ṣiṣẹ́ ní ibi mímọ́ aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n sìn bí àlùfáà.”

20 Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sì kúrò níwájú Mose, 21 Olúkúlùkù ẹni tí ó fẹ́ àti ẹni tí ọkàn rẹ̀ gbé sókè wá, wọ́n sì mú ọrẹ fún Olúwa, fún iṣẹ́ àgọ́ àjọ, fún gbogbo ìsìn rẹ̀ àti fún aṣọ mímọ́ náà. 22 Gbogbo àwọn tí ó fẹ́, ọkùnrin àti obìnrin, wọ́n wá wọ́n sì mú onírúurú ìlẹ̀kẹ̀ wúrà: òrùka etí, òrùka àti ọ̀ṣọ́. Gbogbo wọn mú wúrà gẹ́gẹ́ bí ọrẹ wá fún Olúwa. 23 Olúkúlùkù ẹni tí ó ni aṣọ aláró elése àlùkò, òdòdó àti ọ̀gbọ̀ dáradára, tàbí irun ewúrẹ́, awọ àgbò tí a rì ní pupa tàbí awọ màlúù odò, kí ó mú wọn wá. 24 Àwọn tí ó mú ọrẹ fàdákà tàbí idẹ wá, mú ọrẹ wá fún Olúwa, àti olúkúlùkù ẹni tí ó ní igi ṣittimu fún ipa kankan nínú iṣẹ́ mú un wá. 25 Gbogbo àwọn obìnrin tí ó ní ọgbọ́n ríran owú pẹ̀lú ọwọ́ rẹ̀, kí ó mú èyí ti ó ti ran wá ti aláró, ti elése àlùkò, ti òdòdó tàbí ti ọ̀gbọ̀ dáradára. 26 Gbogbo àwọn obìnrin tí ó fẹ́, tí ó sì ní ọgbọ́n ń ran òwú irun ewúrẹ́ 27 Àwọn olórí mú òkúta óníkìsì wá láti tò ó lórí ẹ̀wù efodu àti ìgbàyà. 28 Wọ́n sì tún mú olóòórùn àti òróró olifi wá fún títanná àti fún òróró ìtasórí àti fún tùràrí dídùn. 29 Gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli ọkùnrin àti obìnrin ẹni tí ó fẹ́ mú ọrẹ àtinúwá fún Olúwa fún gbogbo iṣẹ́ tí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn láti ṣe nípasẹ̀ Mose.

Besaleli àti Oholiabu

30 (C)Nígbà náà ni Mose wí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Wò ó, Olúwa ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda, 31 Ó sì ti fi ẹ̀mí Ọlọ́run kún un, pẹ̀lú ọgbọ́n, òye, ìmọ̀ àti gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà 32 Láti máa ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní ti wúrà, fàdákà àti idẹ, 33 láti gbẹ́ òkúta àti láti tò ó, láti fún igi àti láti ṣiṣẹ́ ni gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà. 34 Ó sì fún òun àti Oholiabu ọmọ Ahisamaki ti ẹ̀yà Dani, ni agbára láti kọ́ àwọn tókù. 35 Ó sì fi ọgbọ́n kún wọn láti ṣe gbogbo onírúurú iṣẹ́, ti oníṣọ̀nà, ti ayàwòrán, ti aránsọ, ti aláṣọ aláró, ti elése àlùkò, ti òdòdó àti ní ọ̀gbọ̀ dáradára àti ti ahunṣọ, gbogbo èyí tí ọ̀gá oníṣẹ́-ọnà àti ayàwòrán ń ṣe.

Sabbath Regulations

35 Moses assembled the whole Israelite community and said to them, “These are the things the Lord has commanded(A) you to do: For six days, work is to be done, but the seventh day shall be your holy day, a day of sabbath(B) rest to the Lord. Whoever does any work on it is to be put to death.(C) Do not light a fire in any of your dwellings on the Sabbath day.(D)

Materials for the Tabernacle(E)(F)

Moses said to the whole Israelite community, “This is what the Lord has commanded: From what you have, take an offering for the Lord. Everyone who is willing is to bring to the Lord an offering of gold, silver and bronze; blue, purple and scarlet yarn and fine linen; goat hair; ram skins dyed red and another type of durable leather[a]; acacia wood; olive oil(G) for the light; spices for the anointing oil and for the fragrant incense; and onyx stones and other gems to be mounted on the ephod and breastpiece.

10 “All who are skilled among you are to come and make everything the Lord has commanded:(H) 11 the tabernacle(I) with its tent and its covering, clasps, frames, crossbars, posts and bases; 12 the ark(J) with its poles and the atonement cover and the curtain(K) that shields it; 13 the table(L) with its poles and all its articles and the bread of the Presence; 14 the lampstand(M) that is for light with its accessories, lamps and oil for the light; 15 the altar(N) of incense with its poles, the anointing oil(O) and the fragrant incense;(P) the curtain for the doorway at the entrance to the tabernacle;(Q) 16 the altar(R) of burnt offering with its bronze grating, its poles and all its utensils; the bronze basin(S) with its stand; 17 the curtains of the courtyard with its posts and bases, and the curtain for the entrance to the courtyard;(T) 18 the tent pegs(U) for the tabernacle and for the courtyard, and their ropes; 19 the woven garments worn for ministering in the sanctuary—both the sacred garments(V) for Aaron the priest and the garments for his sons when they serve as priests.”

20 Then the whole Israelite community withdrew from Moses’ presence, 21 and everyone who was willing and whose heart moved them came and brought an offering to the Lord for the work on the tent of meeting, for all its service, and for the sacred garments. 22 All who were willing, men and women alike, came and brought gold jewelry of all kinds: brooches, earrings, rings and ornaments. They all presented their gold as a wave offering to the Lord. 23 Everyone who had blue, purple or scarlet yarn(W) or fine linen, or goat hair, ram skins dyed red or the other durable leather brought them. 24 Those presenting an offering of silver or bronze brought it as an offering to the Lord, and everyone who had acacia wood for any part of the work brought it. 25 Every skilled woman(X) spun with her hands and brought what she had spun—blue, purple or scarlet yarn or fine linen. 26 And all the women who were willing and had the skill spun the goat hair. 27 The leaders(Y) brought onyx stones and other gems(Z) to be mounted on the ephod and breastpiece. 28 They also brought spices and olive oil for the light and for the anointing oil and for the fragrant incense.(AA) 29 All the Israelite men and women who were willing(AB) brought to the Lord freewill offerings(AC) for all the work the Lord through Moses had commanded them to do.

Bezalel and Oholiab(AD)

30 Then Moses said to the Israelites, “See, the Lord has chosen Bezalel son of Uri, the son of Hur, of the tribe of Judah, 31 and he has filled him with the Spirit of God, with wisdom, with understanding, with knowledge and with all kinds of skills(AE) 32 to make artistic designs for work in gold, silver and bronze, 33 to cut and set stones, to work in wood and to engage in all kinds of artistic crafts. 34 And he has given both him and Oholiab(AF) son of Ahisamak, of the tribe of Dan, the ability to teach(AG) others. 35 He has filled them with skill to do all kinds of work(AH) as engravers, designers, embroiderers in blue, purple and scarlet yarn and fine linen, and weavers—all of them skilled workers and designers.

Footnotes

  1. Exodus 35:7 Possibly the hides of large aquatic mammals; also in verse 23