Add parallel Print Page Options

Òkúta wàláà tuntun

34 Olúwa sọ fún Mose pé, “E gé òkúta wàláà méjì jáde bí i ti àkọ́kọ́, èmi yóò sì kọ àwọn ọ̀rọ̀ ìwé tó wà lára tí àkọ́kọ́ tí ìwọ ti fọ́ sára wọn. Múra ní òwúrọ̀, kí o sì wá sórí òkè Sinai. Kí o fi ara rẹ hàn mí lórí òkè náà. Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá pẹ̀lú rẹ tàbí kí a rí wọn lórí òkè náà; bẹ́ẹ̀ ni agbo àgùntàn tàbí ọwọ́ ẹran kó má ṣe jẹ níwájú òkè náà.”

Bẹ́ẹ̀ Mose sì gbẹ́ òkúta wàláà méjì bí ti àkọ́kọ́, ó sì gun orí òkè Sinai lọ ní kùtùkùtù òwúrọ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un; Ó sì gbé òkúta wàláà méjèèjì náà sí ọwọ́ rẹ̀. Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú àwọsánmọ̀, ó sì dúró níbẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì pòkìkí orúkọ Olúwa. (A)Ó sì kọjá níwájú Mose, ó sì ń ké pé, “Olúwa, Olúwa, Ọlọ́run aláàánú àti olóore-ọ̀fẹ́, ẹni tí ó lọ́ra láti bínú, tí ó pọ̀ ní ìfẹ́ àti olóòtítọ́, Ẹni tí ó ń pa ìfẹ́ mọ́ fún ẹgbẹ̀rún (1,000), ó sì ń dáríjì àwọn ẹni búburú, àwọn ti ń ṣọ̀tẹ̀ àti ẹlẹ́ṣẹ̀. Síbẹ̀ kì í fi àwọn ẹlẹ́bi sílẹ̀ láìjìyà; Ó ń fi ìyà jẹ ọmọ àti àwọn ọmọ wọn fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba dé ìran kẹta àti ẹ̀kẹrin.”

Mose foríbalẹ̀ lẹ́ẹ̀kan náà ó sì sìn. Ó wí pé, “Olúwa, bí èmi bá rí ojúrere rẹ, nígbà náà jẹ́ kí Olúwa lọ pẹ̀lú wa. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, ènìyàn ọlọ́rùn líle ni wọn, dárí búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wa jì, kí o sì gbà wá gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ.”

10 Nígbà náà ni Olúwa wí pé: “Èmi dá májẹ̀mú kan pẹ̀lú yín. Níwájú gbogbo ènìyàn rẹ èmi yóò ṣe ìyanu, tí a kò tí ì ṣe ní orílẹ̀-èdè ní gbogbo ayé rí. Àwọn ènìyàn tí ìwọ ń gbé láàrín wọn yóò rí i bí iṣẹ́ tí èmi Olúwa yóò ṣe fún ọ ti ní ẹ̀rù tó 11 Ṣe ohun tí èmi pàṣẹ fún ọ lónìí. Èmi lé àwọn ará Amori, àwọn ará Kenaani, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hiti, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi jáde níwájú rẹ. 12 Máa ṣọ́ra kí o má ba à bá àwọn ti ó n gbé ilẹ̀ náà tí ìwọ ń lọ dá májẹ̀mú, nítorí wọn yóò jẹ́ ìdẹwò láàrín rẹ. 13 Wó pẹpẹ wọn lulẹ̀, fọ́ òkúta mímọ́ wọn, kí o sì gé òpó Aṣerah wọn. (Ère òrìṣà wọn). 14 (B)Ẹ má ṣe sin ọlọ́run mìíràn, nítorí Olúwa, orúkọ ẹni ti ń jẹ́ Òjòwú, Ọlọ́run owú ni.

15 “Máa ṣọ́ra kí ẹ má ṣe bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ilẹ̀ náà dá májẹ̀mú; nígbà tí wọ́n bá ń ṣe àgbèrè tọ òrìṣà wọn, tí wọ́n sì rú ẹbọ sí wọn, wọn yóò pè yín, ẹ̀yin yóò sì jẹ ẹbọ wọn. 16 Nígbà tí ìwọ bá yàn nínú àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin rẹ ní ìyàwó, àwọn ọmọbìnrin wọ̀nyí yóò ṣe àgbèrè tọ òrìṣà wọn, wọn yóò sì mú kí àwọn ọmọkùnrin yín náà ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.

17 (C)“Ìwọ kò gbọdọ̀ dá ère òrìṣàkórìṣà fún ara rẹ.

18 (D)“Àjọ àkàrà àìwú ni kí ìwọ máa pamọ́. Fún ọjọ́ méje ni ìwọ yóò jẹ àkàrà aláìwú, gẹ́gẹ́ bí èmi ti pa á láṣẹ fún ọ. Ṣe èyí ní ìgbà tí a yàn nínú oṣù Abibu, nítorí ní oṣù náà ni ẹ jáde láti Ejibiti wá.

19 (E)“Gbogbo àkọ́bí inú kọ̀ọ̀kan tèmi ní i ṣe, pẹ̀lú àkọ́bí gbogbo ohun ọ̀sìn rẹ, bóyá ti màlúù tàbí ti àgùntàn. 20 Àkọ́bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ni kí ìwọ kí ó fi ọ̀dọ́-àgùntàn rà padà, ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá rà á padà, dá ọrùn rẹ̀. Ra gbogbo àkọ́bí ọkùnrin rẹ padà.

“Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá síwájú mi ní ọwọ́ òfo.

21 (F)“Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ keje ìwọ yóò sinmi; kódà ní àkókò ìfúnrúgbìn àti ní àkókò ìkórè ìwọ gbọdọ̀ sinmi.

22 (G)“Ṣe àjọ ọ̀sẹ̀ pẹ̀lú àkọ́so èso alikama àti àjọ ìkórè ní òpin ọdún. 23 Ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta lọ́dún, gbogbo àwọn ọkùnrin ni kí ó farahàn níwájú Olúwa Olódùmarè, Ọlọ́run Israẹli. 24 Èmi yóò lé orílẹ̀-èdè jáde níwájú rẹ, èmi yóò sì mú kí ìpín rẹ fẹ̀, ẹnikẹ́ni kì yóò gba ilẹ̀ rẹ nígbà tí ìwọ bá gòkè lọ ní ìgbà mẹ́ta lọ́dún kọ̀ọ̀kan láti farahàn níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.

25 (H)“Má ṣe ta ẹ̀jẹ̀ ẹbọ sí mi pẹ̀lú ohunkóhun tí ó bá ní ìwúkàrà, kí o má sì ṣe jẹ́ kí ẹbọ ìrékọjá kù títí di òwúrọ̀.

26 (I)“Mú àkọ́ká èso ilẹ̀ rẹ tí ó dára jùlọ wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ.

“Ìwọ kò gbọdọ̀ bọ ọmọ ewúrẹ́ nínú omi ọmú ìyá rẹ̀.”

27 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Kọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sílẹ̀, nítorí nípa àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni èmi bá ìwọ àti Israẹli dá májẹ̀mú.” 28 Mose wà níbẹ̀ pẹ̀lú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru (40) láìjẹ oúnjẹ tàbí mu omi. Ó sì kọ ọ̀rọ̀ májẹ̀mú náà òfin mẹ́wàá sára wàláà.

Dídán ojú Mose

29 (J)Nígbà tí Mose sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè Sinai pẹ̀lú wàláà ẹ̀rí méjì ní ọwọ́ rẹ̀, òun kò mọ̀ pé ojú òun ń dán nítorí ó bá Olúwa sọ̀rọ̀. 30 Nígbà tí Aaroni àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli rí Mose, ojú rẹ̀ ń dán, ẹ̀rù sì ń bà wọ́n láti súnmọ́ ọn. 31 Ṣùgbọ́n Mose pè wọn; Aaroni àti gbogbo àwọn olórí àjọ padà wá bá a, ó sì bá wọn sọ̀rọ̀. 32 Lẹ́yìn èyí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli súnmọ́ ọn, ó sì fún wọn ní gbogbo àṣẹ tí Olúwa fún un lórí òkè Sinai.

33 Nígbà tí Mose parí ọ̀rọ̀ sísọ fún wọn. Ó fi ìbòjú bo ojú rẹ̀. 34 Ṣùgbọ́n nígbàkígbà tí Mose bá wà níwájú Olúwa láti bá a sọ̀rọ̀, á ṣí ìbòjú náà títí yóò fi jáde. Nígbà tí ó bá sì jáde, á sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli ohun tí a ti pàṣẹ fún un, 35 Àwọn ọmọ Israẹli sì rí i pé ojú rẹ̀ ń dán. Mose á sì tún fi ìbòjú bo ojú rẹ̀ títí á fi lọ bá Olúwa sọ̀rọ̀.

The New Stone Tablets

34 The Lord said to Moses, “Chisel out two stone tablets like the first ones,(A) and I will write on them the words that were on the first tablets,(B) which you broke.(C) Be ready in the morning, and then come up on Mount Sinai.(D) Present yourself to me there on top of the mountain. No one is to come with you or be seen anywhere on the mountain;(E) not even the flocks and herds may graze in front of the mountain.”

So Moses chiseled(F) out two stone tablets like the first ones and went up Mount Sinai early in the morning, as the Lord had commanded him; and he carried the two stone tablets in his hands.(G) Then the Lord came down in the cloud(H) and stood there with him and proclaimed his name, the Lord.(I) And he passed in front of Moses, proclaiming, “The Lord, the Lord, the compassionate(J) and gracious God, slow to anger,(K) abounding in love(L) and faithfulness,(M) maintaining love to thousands,(N) and forgiving wickedness, rebellion and sin.(O) Yet he does not leave the guilty unpunished;(P) he punishes the children and their children for the sin of the parents to the third and fourth generation.”(Q)

Moses bowed to the ground at once and worshiped. “Lord,” he said, “if I have found favor(R) in your eyes, then let the Lord go with us.(S) Although this is a stiff-necked(T) people, forgive our wickedness and our sin,(U) and take us as your inheritance.”(V)

10 Then the Lord said: “I am making a covenant(W) with you. Before all your people I will do wonders(X) never before done in any nation in all the world.(Y) The people you live among will see how awesome is the work that I, the Lord, will do for you. 11 Obey what I command(Z) you today. I will drive out before you the Amorites, Canaanites, Hittites, Perizzites, Hivites and Jebusites.(AA) 12 Be careful not to make a treaty(AB) with those who live in the land where you are going, or they will be a snare(AC) among you. 13 Break down their altars, smash their sacred stones and cut down their Asherah poles.[a](AD) 14 Do not worship any other god,(AE) for the Lord, whose name(AF) is Jealous, is a jealous God.(AG)

15 “Be careful not to make a treaty(AH) with those who live in the land; for when they prostitute(AI) themselves to their gods and sacrifice to them, they will invite you and you will eat their sacrifices.(AJ) 16 And when you choose some of their daughters as wives(AK) for your sons and those daughters prostitute themselves to their gods,(AL) they will lead your sons to do the same.

17 “Do not make any idols.(AM)

18 “Celebrate the Festival of Unleavened Bread.(AN) For seven days eat bread made without yeast,(AO) as I commanded you. Do this at the appointed time in the month of Aviv,(AP) for in that month you came out of Egypt.

19 “The first offspring(AQ) of every womb belongs to me, including all the firstborn males of your livestock, whether from herd or flock. 20 Redeem the firstborn donkey with a lamb, but if you do not redeem it, break its neck.(AR) Redeem all your firstborn sons.(AS)

“No one is to appear before me empty-handed.(AT)

21 “Six days you shall labor, but on the seventh day you shall rest;(AU) even during the plowing season and harvest(AV) you must rest.

22 “Celebrate the Festival of Weeks with the firstfruits(AW) of the wheat harvest, and the Festival of Ingathering(AX) at the turn of the year.[b] 23 Three times(AY) a year all your men are to appear before the Sovereign Lord, the God of Israel. 24 I will drive out nations(AZ) before you and enlarge your territory,(BA) and no one will covet your land when you go up three times each year to appear before the Lord your God.

25 “Do not offer the blood of a sacrifice to me along with anything containing yeast,(BB) and do not let any of the sacrifice from the Passover Festival remain until morning.(BC)

26 “Bring the best of the firstfruits(BD) of your soil to the house of the Lord your God.

“Do not cook a young goat in its mother’s milk.”(BE)

27 Then the Lord said to Moses, “Write(BF) down these words, for in accordance with these words I have made a covenant(BG) with you and with Israel.” 28 Moses was there with the Lord forty days and forty nights(BH) without eating bread or drinking water.(BI) And he wrote on the tablets(BJ) the words of the covenant—the Ten Commandments.(BK)

The Radiant Face of Moses

29 When Moses came down from Mount Sinai(BL) with the two tablets of the covenant law in his hands,(BM) he was not aware that his face was radiant(BN) because he had spoken with the Lord. 30 When Aaron and all the Israelites saw Moses, his face was radiant, and they were afraid to come near him. 31 But Moses called to them; so Aaron and all the leaders of the community(BO) came back to him, and he spoke to them. 32 Afterward all the Israelites came near him, and he gave them all the commands(BP) the Lord had given him on Mount Sinai.

33 When Moses finished speaking to them, he put a veil(BQ) over his face. 34 But whenever he entered the Lord’s presence to speak with him, he removed the veil until he came out. And when he came out and told the Israelites what he had been commanded, 35 they saw that his face was radiant.(BR) Then Moses would put the veil back over his face until he went in to speak with the Lord.

Footnotes

  1. Exodus 34:13 That is, wooden symbols of the goddess Asherah
  2. Exodus 34:22 That is, in the autumn