Add parallel Print Page Options

Mose bùkún fún àwọn ẹ̀yà

33 Èyí ni ìbùkún tí Mose ènìyàn Ọlọ́run bùkún fún àwọn ọmọ Israẹli kí ó tó kú. Ó sì wí pé:

Olúwa ti Sinai wá,
    ó sì yọ sí wọn láti Seiri wá
    ó sì tàn án jáde láti òkè Parani wá.
Ó ti ọ̀dọ̀ ẹgbẹgbàarùn-ún àwọn mímọ́ wá
    láti ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni òfin kan a mú bí iná ti jáde fún wọn wá.
Nítòótọ́, ó fẹ́ràn àwọn ènìyàn an rẹ̀,
    gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́ wà ní ọwọ́ rẹ̀.
Ní ẹsẹ̀ rẹ̀ ni wọ́n ti foríbalẹ̀,
    àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni wọ́n ti ń gba ọ̀rọ̀,
òfin tí Mose fi fún wa,
    ìní ti ìjọ ènìyàn Jakọbu.
Òun ni ọba lórí Jeṣuruni
    ní ìgbà tí olórí àwọn ènìyàn péjọpọ̀,
    pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Israẹli.

“Jẹ́ kí Reubeni yè kí ó má ṣe kú,
    tàbí kí ènìyàn rẹ mọ níwọ̀n.”

Èyí ni ohun tí ó sọ nípa Juda:

Olúwa gbọ́ ohùn Juda
    kí o sì mú tọ àwọn ènìyàn rẹ̀ wá.
Kí ọwọ́ rẹ̀ kí ó tó fún un,
    kí ó sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀!”

Ní ti Lefi ó wí pé:

“Jẹ́ kí Tumimu àti Urimu rẹ kí ó wà
    pẹ̀lú ẹni mímọ́ rẹ.
Ẹni tí ó dánwò ní Massa,
    ìwọ bá jà ní omi Meriba.
Ó wí fún baba àti ìyá rẹ pé,
    ‘Èmi kò buyì fún wọn.’
Kò mọ àwọn arákùnrin rẹ̀,
    tàbí mọ àwọn ọmọ rẹ̀,
ṣùgbọ́n ó dúró lórí ọ̀rọ̀ rẹ̀,
    ó sì pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́.
10 Ó kọ́ Jakọbu ní ìdájọ́ rẹ̀
    àti Israẹli ní òfin rẹ̀.
Ó mú tùràrí wá síwájú rẹ̀
    àti ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ẹbọ sísun sórí i pẹpẹ rẹ̀.
11 Bùsi ohun ìní rẹ̀, Olúwa,
    kí o sì tẹ́wọ́gbà iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.
Lu ẹgbẹ́ àwọn tí ó dìde sí i;
    àwọn tí ó kórìíra rẹ̀,
    kí wọn kí ó má ṣe dìde mọ́.”

12 Ní ti Benjamini ó wí pé:

“Jẹ́ kí olùfẹ́ Olúwa máa gbé ní àlàáfíà lọ́dọ̀ rẹ̀,
    òun a máa bò ó ní gbogbo ọjọ́,
    ẹni tí Olúwa fẹ́ràn yóò máa sinmi láàrín èjìká rẹ̀.”

13 Ní ti Josẹfu ó wí pé:

“Kí Olúwa bùkún ilẹ̀ rẹ,
    fún ohun iyebíye láti ọ̀run pẹ̀lú ìrì
    àti ibú tí ó ń bẹ níṣàlẹ̀;
14 àti fún èso iyebíye tí ọ̀run mú wá
    àti ti ohun iyebíye tí ń dàgbà ní oṣooṣù;
15 pẹ̀lú ohun pàtàkì òkè ńlá ìgbàanì
    àti fún ohun iyebíye ìgbà ayérayé;
16 Pẹ̀lú ohun iyebíye ayé àti ẹ̀kún un rẹ̀
    àti fún ìfẹ́ ẹni tí ó ń gbé inú igbó.
Jẹ́ kí gbogbo èyí sinmi lé orí Josẹfu,
    lórí àtàrí ẹni tí ó yàtọ̀ láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀.
17 Ní ọláńlá ó dàbí àkọ́bí akọ màlúù;
    ìwo rẹ̀, ìwo àgbáǹréré ni.
Pẹ̀lú wọn ni yóò fi ti àwọn orílẹ̀-èdè,
    pàápàá títí dé òpin ayé.
Àwọn ní ẹgbẹẹgbàárùn-ún (10,000) Efraimu,
    àwọn sì ní ẹgbẹẹgbẹ̀rún (1,000) Manase.”

18 Ní ti Sebuluni ó wí pé:

“Yọ̀ Sebuluni, ní ti ìjáde lọ rẹ,
    àti ìwọ Isakari, nínú àgọ́ rẹ.
19 Wọn yóò pe àwọn ènìyàn sórí òkè
    àti níbẹ̀ wọn yóò rú ẹbọ òdodo,
wọn yóò mu nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ Òkun,
    nínú ìṣúra tí ó pamọ́ nínú iyanrìn.”

20 Ní ti Gadi ó wí pé:

“Ìbùkún ni ẹni tí ó mú Gadi gbilẹ̀!
    Gadi ń gbé níbẹ̀ bí kìnnìún,
    ó sì fa apá ya, àní àtàrí.
21 Ó sì yan ilẹ̀ tí ó dára jù fún ara rẹ̀;
    ìpín olórí ni a sì fi fún un.
Nígbà tí ó rí tí gbogbo àwọn ènìyàn péjọ,
    ó mú òdodo Olúwa ṣẹ,
    àti ìdájọ́ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli.”

22 Ní ti Dani ó wí pé:

“Ọmọ kìnnìún ni Dani,
    tí ń fò láti Baṣani wá.”

23 Ní ti Naftali ó wí pé:

“Ìwọ Naftali, kún fún ojúrere Ọlọ́run
    àti ìbùkún Olúwa;
    yóò jogún ìhà ìwọ̀-oòrùn àti gúúsù.”

24 Ní ti Aṣeri ó wí pé:

“Ìbùkún ọmọ ni ti Aṣeri;
    jẹ́ kí ó rí ojúrere láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀
    kí ó sì ri ẹsẹ̀ rẹ̀ sínú òróró.
25 Bàtà rẹ̀ yóò jẹ́ irin àti idẹ,
    agbára rẹ̀ yóò sì rí bí ọjọ́ rẹ̀.

26 “Kò sí ẹlòmíràn bí Ọlọ́run Jeṣuruni,
    ẹni tí ń gun ọ̀run fún ìrànlọ́wọ́ rẹ
    àti ní ojú ọ̀run nínú ọláńlá rẹ̀.
27 Ọlọ́run ayérayé ni ibi ìsádi rẹ,
    àti ní ìsàlẹ̀ ni apá ayérayé wà.
Yóò lé àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ,
    ó sì wí pé, ‘Ẹ máa parun!’
28 Israẹli nìkan yóò jókòó ní àlàáfíà,
    orísun Jakọbu nìkan
ní ilẹ̀ ọkà àti ti ọtí wáìnì,
    níbi tí ọ̀run ti ń sẹ ìrì sílẹ̀.
29 Ìbùkún ni fún ọ, Israẹli,
    ta ni ó dàbí rẹ,
    ẹni tí a gbàlà láti ọ̀dọ̀ Olúwa?
Òun ni asà àti ìrànwọ́ rẹ̀
    àti idà ọláńlá rẹ̀.
Àwọn ọ̀tá rẹ yóò tẹríba fún ọ,
    ìwọ yóò sì tẹ ibi gíga wọn mọ́lẹ̀.”

Moses Blesses the Tribes(A)

33 This is the blessing(B) that Moses the man of God(C) pronounced on the Israelites before his death. He said:

“The Lord came from Sinai(D)
    and dawned over them from Seir;(E)
    he shone forth(F) from Mount Paran.(G)
He came with[a] myriads of holy ones(H)
    from the south, from his mountain slopes.[b]
Surely it is you who love(I) the people;
    all the holy ones are in your hand.(J)
At your feet they all bow down,(K)
    and from you receive instruction,
the law that Moses gave us,(L)
    the possession of the assembly of Jacob.(M)
He was king(N) over Jeshurun[c](O)
    when the leaders of the people assembled,
    along with the tribes of Israel.

“Let Reuben live and not die,
    nor[d] his people be few.”(P)

And this he said about Judah:(Q)

“Hear, Lord, the cry of Judah;
    bring him to his people.
With his own hands he defends his cause.
    Oh, be his help against his foes!”

About Levi(R) he said:

“Your Thummim and Urim(S) belong
    to your faithful servant.(T)
You tested(U) him at Massah;
    you contended with him at the waters of Meribah.(V)
He said of his father and mother,(W)
    ‘I have no regard for them.’
He did not recognize his brothers
    or acknowledge his own children,
but he watched over your word
    and guarded your covenant.(X)
10 He teaches(Y) your precepts to Jacob
    and your law to Israel.(Z)
He offers incense before you(AA)
    and whole burnt offerings on your altar.(AB)
11 Bless all his skills, Lord,
    and be pleased with the work of his hands.(AC)
Strike down those who rise against him,
    his foes till they rise no more.”

12 About Benjamin(AD) he said:

“Let the beloved of the Lord rest secure in him,(AE)
    for he shields him all day long,(AF)
    and the one the Lord loves(AG) rests between his shoulders.(AH)

13 About Joseph(AI) he said:

“May the Lord bless his land
    with the precious dew from heaven above
    and with the deep waters that lie below;(AJ)
14 with the best the sun brings forth
    and the finest the moon can yield;
15 with the choicest gifts of the ancient mountains(AK)
    and the fruitfulness of the everlasting hills;
16 with the best gifts of the earth and its fullness
    and the favor of him who dwelt in the burning bush.(AL)
Let all these rest on the head of Joseph,
    on the brow of the prince among[e] his brothers.(AM)
17 In majesty he is like a firstborn bull;
    his horns(AN) are the horns of a wild ox.(AO)
With them he will gore(AP) the nations,
    even those at the ends of the earth.
Such are the ten thousands of Ephraim;(AQ)
    such are the thousands of Manasseh.(AR)

18 About Zebulun(AS) he said:

“Rejoice, Zebulun, in your going out,
    and you, Issachar,(AT) in your tents.
19 They will summon peoples to the mountain(AU)
    and there offer the sacrifices of the righteous;(AV)
they will feast on the abundance of the seas,(AW)
    on the treasures hidden in the sand.”

20 About Gad(AX) he said:

“Blessed is he who enlarges Gad’s domain!(AY)
    Gad lives there like a lion,
    tearing at arm or head.
21 He chose the best land for himself;(AZ)
    the leader’s portion was kept for him.(BA)
When the heads of the people assembled,
    he carried out the Lord’s righteous will,(BB)
    and his judgments concerning Israel.”

22 About Dan(BC) he said:

“Dan is a lion’s cub,
    springing out of Bashan.”

23 About Naphtali(BD) he said:

“Naphtali is abounding with the favor of the Lord
    and is full of his blessing;
    he will inherit southward to the lake.”

24 About Asher(BE) he said:

“Most blessed of sons is Asher;
    let him be favored by his brothers,
    and let him bathe his feet in oil.(BF)
25 The bolts of your gates will be iron and bronze,(BG)
    and your strength will equal your days.(BH)

26 “There is no one like the God of Jeshurun,(BI)
    who rides(BJ) across the heavens to help you(BK)
    and on the clouds(BL) in his majesty.(BM)
27 The eternal(BN) God is your refuge,(BO)
    and underneath are the everlasting(BP) arms.
He will drive out your enemies before you,(BQ)
    saying, ‘Destroy them!’(BR)
28 So Israel will live in safety;(BS)
    Jacob will dwell[f] secure
in a land of grain and new wine,
    where the heavens drop dew.(BT)
29 Blessed are you, Israel!(BU)
    Who is like you,(BV)
    a people saved by the Lord?(BW)
He is your shield and helper(BX)
    and your glorious sword.
Your enemies will cower before you,
    and you will tread on their heights.(BY)

Footnotes

  1. Deuteronomy 33:2 Or from
  2. Deuteronomy 33:2 The meaning of the Hebrew for this phrase is uncertain.
  3. Deuteronomy 33:5 Jeshurun means the upright one, that is, Israel; also in verse 26.
  4. Deuteronomy 33:6 Or but let
  5. Deuteronomy 33:16 Or of the one separated from
  6. Deuteronomy 33:28 Septuagint; Hebrew Jacob’s spring is