Add parallel Print Page Options

32 Fetísílẹ̀, Ẹ̀yin ọ̀run, èmi yóò sọ̀rọ̀;
    ẹ gbọ́, ìwọ ayé, ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ ọ̀ mi máa rọ̀ bí òjò,
    kí àwọn ọ̀rọ̀ mi máa sọ̀kalẹ̀ bí ìrì,
bí òjò wíníwíní sára ewéko tuntun,
    bí ọ̀wààrà òjò sára ohun ọ̀gbìn.

Èmi yóò kókìkí orúkọ Olúwa,
    Háà, ẹ yin títóbi Ọlọ́run wa!
Òun ni àpáta, iṣẹ́ ẹ rẹ̀ jẹ́ pípé,
    gbogbo ọ̀nà an rẹ̀ jẹ́ òdodo.
Ọlọ́run olóòtítọ́ tí kò ṣe àṣìṣe kan,
    Ó dúró ṣinṣin, òdodo àti òtítọ́ ni òun.

(A)Wọ́n ti ṣe iṣẹ́ ìbàjẹ́ sọ́dọ̀ ọ rẹ̀;
    fún ìtìjú u wọn, wọn kì í ṣe ọmọ rẹ̀ mọ́,
    ṣùgbọ́n ìran tí ó yí sí apá kan tí ó sì dorí kodò.
Ṣé báyìí ni ẹ̀yin yóò ṣe san an fún Olúwa,
    Háà, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìgbọ́n ènìyàn?
Ǹjẹ́ òun kọ́ ni baba yín, Ẹlẹ́dàá yín,
    tí ó dá a yín tí ó sì mọ yín?

Rántí ìgbà láéláé;
    wádìí àwọn ìran tí ó ti kọjá.
Béèrè lọ́wọ́ baba à rẹ yóò sì sọ fún ọ,
    àwọn àgbàgbà rẹ, wọn yóò sì ṣàlàyé fún ọ.
Nígbà tí Ọ̀gá-ògo fi ogún àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn,
    nígbà tí ó pín onírúurú ènìyàn,
ó sì gbé ààlà kalẹ̀ fún àwọn ènìyàn
    gẹ́gẹ́ bí iye ọmọkùnrin Israẹli.
Nítorí ìpín Olúwa ni àwọn ènìyàn an rẹ̀,
    Jakọbu ni ìpín ìní i rẹ̀.

10 Ní aginjù ni ó ti rí i,
    ní aginjù níbi tí ẹranko kò sí.
Ó yíká, ó sì tọ́jú rẹ̀,
    ó pa á mọ́ bí ẹyin ojú u rẹ̀.
11 Bí idì ti í ru ìtẹ́ rẹ̀ ti ó sì ń
    rábàbà sórí ọmọ rẹ̀,
tí ó na ìyẹ́ apá rẹ̀ láti gbé wọn ki ó sì
    gbé wọn sórí ìyẹ́ apá rẹ̀.
12 Olúwa ṣamọ̀nà;
    kò sì sí ọlọ́run àjèjì pẹ̀lú rẹ̀.

13 Ó mú gun ibi gíga ayé
    ó sì fi èso oko bọ́ ọ.
Ó sì jẹ́ kí ó mú oyin láti inú àpáta wá,
    àti òróró láti inú akọ òkúta wá,
14 Pẹ̀lú u wàràǹkàṣì àti wàrà àgùntàn
    àti ti àgbò ẹran
àti pẹ̀lú ọ̀rá ọ̀dọ́-àgùntàn àti ewúrẹ́,
    pẹ̀lú àgbò irú u ti Baṣani
tí ó sì mu ẹ̀jẹ̀ èso àjàrà, àní àti wáìnì.

15 Jeṣuruni sanra tán ó sì tàpá;
    ìwọ sanra tán, ìwọ ki tan, ọ̀rá sì bò ọ́ tán.
O kọ Ọlọ́run tí ó dá ọ
    o sì kọ àpáta ìgbàlà rẹ.
16 Wọ́n sì fi òrìṣà mú un jowú,
    ohun ìríra ni wọ́n fi mú un bínú.
17 Wọ́n rú ẹbọ sí iwin búburú, tí kì í ṣe Ọlọ́run,
    ọlọ́run tí wọn kò mọ̀ rí,
    ọlọ́run tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ farahàn láìpẹ́,
    ọlọ́run tí àwọn baba yín kò bẹ̀rù.
18 Ìwọ kò rántí àpáta, tí ó bí ọ;
    o sì gbàgbé Ọlọ́run tí ó dá ọ.

19 Olúwa sì rí èyí ó sì kọ̀ wọ́n,
    nítorí tí ó ti bínú nítorí ìwà ìmúnibínú àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ.
20 Ó sì wí pé, “Èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò lára wọn,
    èmi yóò sì wò ó bí ìgbẹ̀yìn in wọn yóò ti rí;
nítorí wọ́n jẹ́ ìran alágídí,
    àwọn ọmọ tí kò sí ìgbàgbọ́ nínú wọn.
21 (B)Wọ́n fi mí jowú nípa ohun tí kì í ṣe Ọlọ́run,
    wọ́n sì fi ohun asán an wọn mú mi bínú.
Èmi yóò mú wọn kún fún ìlara láti ọ̀dọ̀ àwọn tí kì í ṣe ènìyàn;
    èmi yóò sì mú wọn bínú láti ọ̀dọ̀ aṣiwèrè orílẹ̀-èdè.
22 Nítorí pé iná kan ràn nínú ìbínú mi,
    yóò sì jó dé ipò ikú ní ìsàlẹ̀.
Yóò sì run ayé àti ìkórè e rẹ̀
    yóò sì tiná bọ ìpìlẹ̀ àwọn òkè ńlá.

23 “Èmi yóò kó àwọn ohun búburú lé wọn lórí
    èmi ó sì na ọfà mi tán sí wọn lára.
24 Èmi yóò mú wọn gbẹ,
    ooru gbígbóná àti ìparun kíkorò ni a ó fi run wọ́n.
Pẹ̀lú oró ohun tí ń rákò nínú erùpẹ̀.
25 Idà ní òde, àti ẹ̀rù nínú ìyẹ̀wù,
    ni yóò run ọmọkùnrin àti wúńdíá.
Ọmọ ẹnu ọmú àti arúgbó eléwú irun pẹ̀lú.
26 Mo ní èmi yóò tú wọn ká
    èmi yóò sì mú ìrántí i wọn dà kúrò nínú àwọn ènìyàn,
27 nítorí bí mo ti bẹ̀rù ìbínú ọ̀tá,
    kí àwọn ọ̀tá a wọn kí ó má
ba à wí pé, ‘Ọwọ́ wa lékè ni;
    kì í sì í ṣe Olúwa ni ó ṣe gbogbo èyí.’ ”

28 Wọ́n jẹ́ orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀,
    bẹ́ẹ̀ ni kò sí òye nínú wọn.
29 Bí ó ṣe pé wọ́n gbọ́n, kí òye yìí sì yé wọn
    kí wọn ro bí ìgbẹ̀yìn wọn yóò ti rí!
30 Báwo ni ẹnìkan ṣe lè lé ẹgbẹ̀rún,
    tàbí tí ẹni méjì sì lè lé ẹgbàárùn-ún sá,
bí kò ṣe pé àpáta wọn ti tà wọ́n,
    bí kò ṣe pé Olúwa wọn ti fi wọ́n tọrẹ?
31 Nítorí pé àpáta wọn kò dàbí àpáta wa,
    àní àwọn ọ̀tá wa tìkára wọn ń ṣe onídàájọ́.
32 Igi àjàrà a wọn wá láti igi àjàrà Sodomu
    àti ti ìgbẹ́ ẹ Gomorra.
Èso àjàrà wọn kún fún oró,
    Ìdì wọn korò.
33 Ọtí wáìnì wọn ìwọ ti dragoni ni,
    àti oró mímú ti ejò paramọ́lẹ̀.

34 “Èmi kò to èyí jọ ní ìpamọ́
    èmi kò sì fi èdìdì dì í ní ìṣúra mi?
35 Ti èmi ni láti gbẹ̀san; Èmi yóò san án fún wọn
    ní àkókò tí ẹ̀ṣẹ̀ wọn yóò yọ;
ọjọ́ ìdààmú wọn súnmọ́ etílé
    ohun tí ó sì ń bọ̀ wá bá wọn yára bọ̀.”

36 Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn an rẹ̀
    yóò sì ṣàánú fún àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀
nígbà tí ó bá rí i pé agbára wọn lọ tán
    tí kò sì sí ẹnìkan tí ó kù, ẹrú tàbí ọmọ.
37 Yóò wí pé: “Òrìṣà wọn dà báyìí,
    àpáta tí wọ́n fi ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé e wọn,
38 ọlọ́run tí ó jẹ ọ̀rá ẹran ẹbọ wọn
    tí ó ti mu ọtí i wáìnì ẹbọ ohun mímu wọn?
Jẹ́ kí wọn dìde láti gbà wọ́n!
    Jẹ́ kí wọn ṣe ààbò fún un yín!

39 “Wò ó báyìí pé: èmi fúnra à mi, èmi ni!
    Kò sí ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi.
Mo sọ di kíkú mo sì tún sọ di ààyè,
    Mo ti ṣá lọ́gbẹ́ Èmi yóò sì mu jiná,
    kò sí ẹni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ ọ̀ mi.
40 Mo gbé ọwọ́ mi sókè ọ̀run mo sì wí pé:
    Èmi ti wà láààyè títí láé,
41 nígbà tí mo bá pọ́n idà dídán mi
    àti tí mo bá sì fi ọwọ́ mi lé ìdájọ́,
Èmi yóò san ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá mi
    Èmi kò sì san fún àwọn tí ó kórìíra à mi.
42 Èmi yóò mú ọfà mu ẹ̀jẹ̀,
    nígbà tí idà mi bá jẹ ẹran:
ẹ̀jẹ̀ ẹni pípa àti ẹni ìgbèkùn,
    láti orí àwọn aṣáájú ọ̀tá.”

43 (C)Ẹ yọ̀ ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀
    nítorí òun yóò gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀;
yóò sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá a rẹ̀
    yóò sì ṣe ètùtù fún ilẹ̀ àti ènìyàn rẹ̀.

44 Mose sì wá ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí ní etí àwọn ènìyàn náà, òun, àti Hosea ọmọ Nuni. 45 Nígbà tí Mose parí i kíka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí Israẹli. 46 Ó sọ fún un pé, “Ẹ gbé ọkàn an yín lé gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ láàrín yín lónìí, kí ẹ̀yin lè pàṣẹ fún àwọn ọmọ yín láti gbọ́rọ̀ àti láti ṣe gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí. 47 Wọn kì í ṣe ọ̀rọ̀ asán fún ọ, ìyè e yín ni wọ́n. Nípa wọn ni ẹ̀yin yóò gbé pẹ́ lórí ilẹ̀ tí ẹ̀yin ń gòkè e Jordani lọ láti gbà.”

Ikú Mose lórí òkè Nebo

48 Ní ọjọ́ kan náà, Olúwa sọ fún Mose pé, 49 “Gòkè lọ sí Abarimu sí òkè Nebo ní Moabu, tí ó kọjú sí Jeriko, kí o sì wo ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí mo ń fi fún àwọn ọmọ Israẹli, bí ìní i wọn. 50 Ní orí òkè tí ìwọ ń gùn lọ ìwọ yóò kùú níbẹ̀, kí a sì sin ọ́ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ, gẹ́gẹ́ bí arákùnrin in rẹ Aaroni ti kú ní orí òkè Hori tí a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn an rẹ̀. 51 Ìdí ni pé ẹ̀yin méjèèjì ṣẹ̀ sí mi láàrín àwọn ọmọ Israẹli ní ibi omi Meriba Kadeṣi ní aginjù Sini àti nítorí ẹ̀yin kò yà mí sí mímọ́ láàrín àwọn ọmọ Israẹli. 52 Nítorí náà, ìwọ yóò rí ilẹ̀ náà ní ọ̀kánkán, o kì yóò wọ inú rẹ̀ ilẹ̀ ti mo ti fi fún àwọn ọmọ Israẹli.”

32 Listen,(A) you heavens,(B) and I will speak;
    hear, you earth, the words of my mouth.(C)
Let my teaching fall like rain(D)
    and my words descend like dew,(E)
like showers(F) on new grass,
    like abundant rain on tender plants.

I will proclaim(G) the name of the Lord.(H)
    Oh, praise the greatness(I) of our God!
He is the Rock,(J) his works are perfect,(K)
    and all his ways are just.
A faithful God(L) who does no wrong,
    upright(M) and just is he.(N)

They are corrupt and not his children;
    to their shame they are a warped and crooked generation.(O)
Is this the way you repay(P) the Lord,
    you foolish(Q) and unwise people?(R)
Is he not your Father,(S) your Creator,[a]
    who made you and formed you?(T)

Remember the days of old;(U)
    consider the generations long past.(V)
Ask your father and he will tell you,
    your elders, and they will explain to you.(W)
When the Most High(X) gave the nations their inheritance,
    when he divided all mankind,(Y)
he set up boundaries(Z) for the peoples
    according to the number of the sons of Israel.[b](AA)
For the Lord’s portion(AB) is his people,
    Jacob his allotted inheritance.(AC)

10 In a desert(AD) land he found him,
    in a barren and howling waste.(AE)
He shielded(AF) him and cared for him;
    he guarded him as the apple of his eye,(AG)
11 like an eagle that stirs up its nest
    and hovers over its young,(AH)
that spreads its wings to catch them
    and carries them aloft.(AI)
12 The Lord alone led(AJ) him;(AK)
    no foreign god was with him.(AL)

13 He made him ride on the heights(AM) of the land
    and fed him with the fruit of the fields.
He nourished him with honey from the rock,(AN)
    and with oil(AO) from the flinty crag,
14 with curds and milk from herd and flock
    and with fattened lambs and goats,
with choice rams of Bashan(AP)
    and the finest kernels of wheat.(AQ)
You drank the foaming blood of the grape.(AR)

15 Jeshurun[c](AS) grew fat(AT) and kicked;
    filled with food, they became heavy and sleek.
They abandoned(AU) the God who made them
    and rejected the Rock(AV) their Savior.
16 They made him jealous(AW) with their foreign gods
    and angered(AX) him with their detestable idols.
17 They sacrificed(AY) to false gods,(AZ) which are not God—
    gods they had not known,(BA)
    gods that recently appeared,(BB)
    gods your ancestors did not fear.
18 You deserted the Rock, who fathered you;
    you forgot(BC) the God who gave you birth.

19 The Lord saw this and rejected them(BD)
    because he was angered by his sons and daughters.(BE)
20 “I will hide my face(BF) from them,” he said,
    “and see what their end will be;
for they are a perverse generation,(BG)
    children who are unfaithful.(BH)
21 They made me jealous(BI) by what is no god
    and angered me with their worthless idols.(BJ)
I will make them envious by those who are not a people;
    I will make them angry by a nation that has no understanding.(BK)
22 For a fire will be kindled by my wrath,(BL)
    one that burns down to the realm of the dead below.(BM)
It will devour(BN) the earth and its harvests(BO)
    and set afire the foundations of the mountains.(BP)

23 “I will heap calamities(BQ) on them
    and spend my arrows(BR) against them.
24 I will send wasting famine(BS) against them,
    consuming pestilence(BT) and deadly plague;(BU)
I will send against them the fangs of wild beasts,(BV)
    the venom of vipers(BW) that glide in the dust.(BX)
25 In the street the sword will make them childless;
    in their homes terror(BY) will reign.(BZ)
The young men and young women will perish,
    the infants and those with gray hair.(CA)
26 I said I would scatter(CB) them
    and erase their name from human memory,(CC)
27 but I dreaded the taunt of the enemy,
    lest the adversary misunderstand(CD)
and say, ‘Our hand has triumphed;
    the Lord has not done all this.’”(CE)

28 They are a nation without sense,
    there is no discernment(CF) in them.
29 If only they were wise and would understand this(CG)
    and discern what their end will be!(CH)
30 How could one man chase a thousand,
    or two put ten thousand to flight,(CI)
unless their Rock had sold them,(CJ)
    unless the Lord had given them up?(CK)
31 For their rock is not like our Rock,(CL)
    as even our enemies concede.(CM)
32 Their vine comes from the vine of Sodom(CN)
    and from the fields of Gomorrah.
Their grapes are filled with poison,(CO)
    and their clusters with bitterness.(CP)
33 Their wine is the venom of serpents,
    the deadly poison of cobras.(CQ)

34 “Have I not kept this in reserve
    and sealed it in my vaults?(CR)
35 It is mine to avenge;(CS) I will repay.(CT)
    In due time their foot will slip;(CU)
their day of disaster is near
    and their doom rushes upon them.(CV)

36 The Lord will vindicate his people(CW)
    and relent(CX) concerning his servants(CY)
when he sees their strength is gone
    and no one is left, slave(CZ) or free.[d]
37 He will say: “Now where are their gods,
    the rock they took refuge in,(DA)
38 the gods who ate the fat of their sacrifices
    and drank the wine of their drink offerings?(DB)
Let them rise up to help you!
    Let them give you shelter!

39 “See now that I myself am he!(DC)
    There is no god besides me.(DD)
I put to death(DE) and I bring to life,(DF)
    I have wounded and I will heal,(DG)
    and no one can deliver out of my hand.(DH)
40 I lift my hand(DI) to heaven and solemnly swear:
    As surely as I live forever,(DJ)
41 when I sharpen my flashing sword(DK)
    and my hand grasps it in judgment,
I will take vengeance(DL) on my adversaries
    and repay those who hate me.(DM)
42 I will make my arrows drunk with blood,(DN)
    while my sword devours flesh:(DO)
the blood of the slain and the captives,
    the heads of the enemy leaders.”

43 Rejoice,(DP) you nations, with his people,[e][f]
    for he will avenge the blood of his servants;(DQ)
he will take vengeance on his enemies(DR)
    and make atonement for his land and people.(DS)

44 Moses came with Joshua[g](DT) son of Nun and spoke all the words of this song in the hearing of the people. 45 When Moses finished reciting all these words to all Israel, 46 he said to them, “Take to heart all the words I have solemnly declared to you this day,(DU) so that you may command(DV) your children to obey carefully all the words of this law. 47 They are not just idle words for you—they are your life.(DW) By them you will live long(DX) in the land you are crossing the Jordan to possess.”

Moses to Die on Mount Nebo

48 On that same day the Lord told Moses,(DY) 49 “Go up into the Abarim(DZ) Range to Mount Nebo(EA) in Moab, across from Jericho,(EB) and view Canaan,(EC) the land I am giving the Israelites as their own possession. 50 There on the mountain that you have climbed you will die(ED) and be gathered to your people, just as your brother Aaron died(EE) on Mount Hor(EF) and was gathered to his people. 51 This is because both of you broke faith with me in the presence of the Israelites at the waters of Meribah Kadesh(EG) in the Desert of Zin(EH) and because you did not uphold my holiness among the Israelites.(EI) 52 Therefore, you will see the land only from a distance;(EJ) you will not enter(EK) the land I am giving to the people of Israel.”

Footnotes

  1. Deuteronomy 32:6 Or Father, who bought you
  2. Deuteronomy 32:8 Masoretic Text; Dead Sea Scrolls (see also Septuagint) sons of God
  3. Deuteronomy 32:15 Jeshurun means the upright one, that is, Israel.
  4. Deuteronomy 32:36 Or and they are without a ruler or leader
  5. Deuteronomy 32:43 Or Make his people rejoice, you nations
  6. Deuteronomy 32:43 Masoretic Text; Dead Sea Scrolls (see also Septuagint) people, / and let all the angels worship him, /
  7. Deuteronomy 32:44 Hebrew Hoshea, a variant of Joshua