Add parallel Print Page Options

Israẹli kò yípadà sí Ọlọ́run

Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ẹ̀yin màlúù Baṣani lórí òkè Samaria,
    ẹ̀yin obìnrin tí ó ń ni tálákà lára,
    tí ó ń tẹ aláìní mọ́lẹ̀, tí ó wí fún ọkọ rẹ̀, “Gbé wá kí a sì mu!”
Olúwa Olódùmarè ti fi ìwà mímọ́ rẹ̀ búra:
    “Àkókò náà yóò dé nítòótọ́
nígbà tí a ó fi ìwọ̀ mú un yín lọ,
    ẹni tí ó kẹ́yìn pẹ̀lú ìwọ̀ ẹja.
Ẹni kọ̀ọ̀kan yín yóò jáde lọ
    gba àárín odi yíya
    a ó sì lé e yín sí Harmoni,”
    ni Olúwa wí.
“Ẹ lọ sí Beteli láti dẹ́ṣẹ̀;
    ẹ lọ sí Gilgali kí ẹ sì dẹ́ṣẹ̀ sí i.
Ẹ mú ẹbọ sísun yín láràárọ̀ wá,
    ìdámẹ́wàá yín ní ọdọọdún mẹ́ta.
Kí ẹ mú ọ̀rẹ́ ìdúpẹ́ ìyẹ̀fun ìwúkàrà ti a sun
    kí ẹ sì mú ọrẹ àtinúwá
lọ fi wọ́n yangàn, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli,
    nítorí èyí ni ẹ fẹ́ láti ṣe,”
    ni Olúwa Olódùmarè wí.

“Èmi fún un yín ní mímọ́ eyín ní gbogbo ìlú yín,
    àti àìní oúnjẹ ní gbogbo ibùgbé yín,
    síbẹ̀, ẹ̀yin kò yípadà sọ́dọ̀ mi,”
    ni Olúwa wí.

“Àti pẹ̀lú mo mú òjò dúró
    nígbà tí ìkórè ku oṣù mẹ́ta.
Mo rán òjò sí ibùgbé kan
    ṣùgbọ́n kò rọ̀ sí ìlú mìíràn.
Oko kan ní òjò;
    àwọn mìíràn kò ní ó sì gbẹ.
Àwọn ènìyàn ń rìn láti ìlú kan sí ìlú mìíràn fún omi
    wọn kò rí mu tẹ́ wọn lọ́rùn,
    síbẹ̀ ẹ̀yin kò padà sí ọ̀dọ̀ mi,”
    ni Olúwa wí.

“Lọ́pọ̀ ìgbà ni mo kọlu ọgbà àti ọgbà àjàrà yín
    mo fi ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù lù wọ́n.
Eṣú sì jẹ igi ọ̀pọ̀tọ́ àti igi olifi yín,
    síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,”
    ni Olúwa wí.

10 “Mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn sí i yín
    bí mo ti ṣe sí Ejibiti.
Mo fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín.
    Pẹ̀lú àwọn ẹṣin tí a kó ní ìgbèkùn.
Mo kún imú yín fún òórùn ibùdó yín,
    síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,”
    ni Olúwa wí.

11 “Mo ti bì ṣubú nínú yín,
    bí Ọlọ́run ti bi Sodomu àti Gomorra ṣubú
ẹ̀yin sì dàbí ògúnná tí a fa yọ kúrò nínú iná,
    síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,”
    ni Olúwa wí.

12 “Nítorí náà, èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí i yín, Israẹli,
    àti nítorí tí èmi ó ṣe èyí sí i yín,
    ẹ múra láti pàdé Ọlọ́run yín, ẹ̀yin Israẹli.”

13 Ẹni tí ó dá àwọn òkè
    tí ó dá afẹ́fẹ́
    tí ó sì fi èrò rẹ̀ hàn sí ènìyàn,
ẹni tí ó yípadà sí òkùnkùn
    tí ó sì tẹ ibi gíga ayé.
    Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.

Israel Has Not Returned to God

Hear this word, you cows of Bashan(A) on Mount Samaria,(B)
    you women who oppress the poor(C) and crush the needy(D)
    and say to your husbands,(E) “Bring us some drinks!(F)
The Sovereign Lord has sworn by his holiness:
    “The time(G) will surely come
when you will be taken away(H) with hooks,(I)
    the last of you with fishhooks.[a]
You will each go straight out
    through breaches in the wall,(J)
    and you will be cast out toward Harmon,[b]
declares the Lord.
“Go to Bethel(K) and sin;
    go to Gilgal(L) and sin yet more.
Bring your sacrifices every morning,(M)
    your tithes(N) every three years.[c](O)
Burn leavened bread(P) as a thank offering
    and brag about your freewill offerings(Q)
boast about them, you Israelites,
    for this is what you love to do,”
declares the Sovereign Lord.

“I gave you empty stomachs in every city
    and lack of bread in every town,
    yet you have not returned to me,”
declares the Lord.(R)

“I also withheld(S) rain from you
    when the harvest was still three months away.
I sent rain on one town,
    but withheld it from another.(T)
One field had rain;
    another had none and dried up.
People staggered from town to town for water(U)
    but did not get enough(V) to drink,
    yet you have not returned(W) to me,”
declares the Lord.(X)

“Many times I struck your gardens and vineyards,
    destroying them with blight and mildew.(Y)
Locusts(Z) devoured your fig and olive trees,(AA)
    yet you have not returned(AB) to me,”
declares the Lord.

10 “I sent plagues(AC) among you
    as I did to Egypt.(AD)
I killed your young men(AE) with the sword,
    along with your captured horses.
I filled your nostrils with the stench(AF) of your camps,
    yet you have not returned to me,”(AG)
declares the Lord.(AH)

11 “I overthrew some of you
    as I overthrew Sodom and Gomorrah.(AI)
You were like a burning stick(AJ) snatched from the fire,
    yet you have not returned to me,”
declares the Lord.(AK)

12 “Therefore this is what I will do to you, Israel,
    and because I will do this to you, Israel,
    prepare to meet your God.”

13 He who forms the mountains,(AL)
    who creates the wind,(AM)
    and who reveals his thoughts(AN) to mankind,
who turns dawn to darkness,
    and treads on the heights of the earth(AO)
    the Lord God Almighty is his name.(AP)

Footnotes

  1. Amos 4:2 Or away in baskets, / the last of you in fish baskets
  2. Amos 4:3 Masoretic Text; with a different word division of the Hebrew (see Septuagint) out, you mountain of oppression
  3. Amos 4:4 Or days