Add parallel Print Page Options

(A)Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Moabu,
    àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà,
Nítorí ó ti sun ún, di eérú,
    egungun ọba Edomu
Èmi yóò rán iná sí orí Moabu
    èyí tí yóò jó àwọn ààfin Kerioti run.
Moabu yóò sì kú pẹ̀lú ariwo
    pẹ̀lú igbe àti pẹ̀lú ìró ìpè
Èmi yóò ké onídàájọ́ rẹ̀ kúrò
    Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn ọmọ-aládé rẹ́ nínú rẹ̀,”
    ni Olúwa wí.

Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Juda,
    àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà
Nítorí wọn ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀
    wọn kò sì pa àwọn ìlànà rẹ̀ mọ́
Nítorí àwọn òrìṣà ti sì wọ́n lọ́nà
    òrìṣà tí àwọn Baba ńlá wọn ń tẹ̀lé
Èmi yóò rán iná sí orí Juda
    èyí tí yóò jó àwọn ààfin Jerusalẹmu run.”

Ìdájọ́ tí yóò wá sórí Israẹli

Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Israẹli
    àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà.
Wọ́n ta olódodo fún fàdákà
    àti aláìní fún bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì.
Wọ́n fi ẹsẹ̀ tẹ orí àwọn tálákà mọ́lẹ̀
    bí wọ́n ti ń tẹ erùpẹ̀ ilẹ̀
    tí wọ́n ko sì ṣe òtítọ́ si àwọn tí a ni lára
Baba àti ọmọ ń wọlé tọ wúńdíá kan náà
    Láti ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́
Wọ́n dùbúlẹ̀ lẹ́bàá a pẹpẹ
    Lórí aṣọ tí wọ́n ti jẹ́ ẹ̀jẹ́
ní ilé òrìṣà wọn
    wọ́n sì mu ọtí tí wọ́n san fún ìtánràn.

“Mo pa àwọn ará Amori run níwájú wọn
    gíga ẹni tí ó dàbí igi kedari.
    Òun sì le koko bí igi óákù
mo pa èso rẹ̀ run láti òkè wá
    àti egbò rẹ̀ láti ìsàlẹ̀ wá.
10 Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá,
    mo sì sìn yín la aginjù já ní ogójì ọdún
    láti fi ilẹ̀ àwọn ará Amori fún un yín.

11 “Èmi sì tún gbé àwọn wòlíì dìde láàrín àwọn ọmọ yín
    àti láàrín àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín láti jẹ Nasiri
èyí kò ha jẹ́ òtítọ́ bí ará Israẹli?”
    ni Olúwa wí.
12 “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin fún àwọn Nasiri ní ọtí mu
    e sì pàṣẹ fún àwọn wòlíì kí wọ́n má ṣe sọtẹ́lẹ̀.

13 “Ní báyìí, èmi yóò tẹ̀ yín mọ́lẹ̀
    bí kẹ̀kẹ́ tí ó kún fún ìtí ti í tẹ̀.
14 Ẹni tí ó yára bí àṣá kò ní rí ọ̀nà àbáyọ
    alágbára kò ní le è dúró lé agbára rẹ̀
    jagunjagun kì yóò le gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là
15 Tafàtafà kì yóò dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀
    bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó gún ẹṣin
    kì yóò gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là
16 Àní jagunjagun tí ó gbóyà jùlọ
    yóò sálọ ní ìhòhò ní ọjọ́ náà,”
    ni Olúwa wí.

This is what the Lord says:

“For three sins of Moab,(A)
    even for four, I will not relent.
Because he burned to ashes(B)
    the bones of Edom’s king,
I will send fire on Moab
    that will consume the fortresses of Kerioth.[a](C)
Moab will go down in great tumult
    amid war cries(D) and the blast of the trumpet.(E)
I will destroy her ruler(F)
    and kill all her officials with him,”(G)
says the Lord.(H)

This is what the Lord says:

“For three sins of Judah,(I)
    even for four, I will not relent.
Because they have rejected the law(J) of the Lord
    and have not kept his decrees,(K)
because they have been led astray(L) by false gods,[b](M)
    the gods[c] their ancestors followed,(N)
I will send fire(O) on Judah
    that will consume the fortresses(P) of Jerusalem.(Q)

Judgment on Israel

This is what the Lord says:

“For three sins of Israel,
    even for four, I will not relent.(R)
They sell the innocent for silver,
    and the needy for a pair of sandals.(S)
They trample on the heads of the poor
    as on the dust of the ground
    and deny justice to the oppressed.
Father and son use the same girl
    and so profane my holy name.(T)
They lie down beside every altar
    on garments taken in pledge.(U)
In the house of their god
    they drink wine(V) taken as fines.(W)

“Yet I destroyed the Amorites(X) before them,
    though they were tall(Y) as the cedars
    and strong as the oaks.(Z)
I destroyed their fruit above
    and their roots(AA) below.
10 I brought you up out of Egypt(AB)
    and led(AC) you forty years in the wilderness(AD)
    to give you the land of the Amorites.(AE)

11 “I also raised up prophets(AF) from among your children
    and Nazirites(AG) from among your youths.
Is this not true, people of Israel?”
declares the Lord.
12 “But you made the Nazirites drink wine
    and commanded the prophets not to prophesy.(AH)

13 “Now then, I will crush you
    as a cart crushes when loaded with grain.(AI)
14 The swift will not escape,(AJ)
    the strong(AK) will not muster their strength,
    and the warrior will not save his life.(AL)
15 The archer(AM) will not stand his ground,
    the fleet-footed soldier will not get away,
    and the horseman(AN) will not save his life.(AO)
16 Even the bravest warriors(AP)
    will flee naked on that day,”
declares the Lord.

Footnotes

  1. Amos 2:2 Or of her cities
  2. Amos 2:4 Or by lies
  3. Amos 2:4 Or lies