Add parallel Print Page Options

Orin ìyìn Dafidi

22 Dafidi sì kọ ọ̀rọ̀ orin yìí sí Olúwa ní ọjọ́ tí Olúwa gbà á kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀, àti kúrò lọ́wọ́ Saulu. (A)Ó sì wí pé:

Olúwa ni àpáta mi, àti Olùgbàlà mi;
    Ọlọ́run mi, àpáta mi, nínú ẹni tí èmi ní ààbò,
    àti ìwo ìgbàlà mi, ibi ìsádi gíga mi.
Àti ibi ìlùmọ̀ mi, Olùgbàlà mi;
    ìwọ ni ó ti gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìwà ipá.

“Èmi ké pe Olúwa, tí ó yẹ láti máa yìn,
    ó sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.
Nígbà tí ìbìlù ìrora ikú yí mi káàkiri;
    tí àwọn ìṣàn ènìyàn búburú dẹ́rùbà mí.
Ọ̀já isà òkú yí mi káàkiri;
    ìkẹ́kùn ikú dojúkọ mí.

“Nínú ìpọ́njú mi, èmi ké pé Olúwa,
    èmi sì gbé ohùn mi sókè sí Ọlọ́run mi.
Ó sí gbóhùn mi láti tẹmpili rẹ̀
    igbe mí wọ etí rẹ̀.
Ilẹ̀ sì mì, ó sì wárìrì;
    ìpìlẹ̀ ọ̀run wárìrì,
    ó sì mì, nítorí tí ó bínú.
Èéfín ti ihò imú rẹ̀ jáde wá;
    Iná ajónirun ti ẹnu rẹ̀ jáde wá,
    ẹ̀yin iná bú jáde láti inú rẹ̀.
10 Ó tẹ orí ọ̀run ba pẹ̀lú, ó sì sọ̀kalẹ̀;
    òkùnkùn biribiri sì ń bẹ ní àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀.
11 Ó sì gun orí kérúbù, ó sì fò:
    a sì rí i lórí ìyẹ́ afẹ́fẹ́.
12 Ó sì fi òkùnkùn ṣe ibùjókòó yí ara rẹ̀, àti àgbájọ omi,
    àní ìṣúdudu ìkùùkuu àwọ̀ sánmọ̀.
13 Nípasẹ̀ ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ̀
    ẹ̀yín iná ràn.
14 Olúwa sán àrá láti ọ̀run wá,
    Ọ̀gá-ògo jùlọ sì fọhùn rẹ̀.
15 Ó sì ta ọfà, ó sì tú wọn ká;
    ó kọ mànàmànà, ó sì ṣẹ́ wọn.
16 Ìṣàn ibú Òkun sì fi ara hàn,
    ìpìlẹ̀ ayé fi ara hàn,
nípa ìbáwí Olúwa,
    nípa fífún èémí ihò imú rẹ̀.

17 “Ó ránṣẹ́ láti òkè wá, ó mú mi;
    ó fà mí jáde láti inú omi ńlá wá.
18 Ó gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá mi alágbára,
    lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi: nítorí pé wọ́n lágbára jù mí lọ.
19 Wọ́n wá láti borí mi lọ́jọ́ ìpọ́njú mi:
    ṣùgbọ́n Olúwa ni aláfẹ̀yìntì mi.
20 Ó sì mú mi wá sí ààyè ńlá:
    ó gbà mi, nítorí tí inú rẹ̀ dún sí mi.

21 Olúwa sán án fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi;
    ó sì san án fún mi gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi.
22 Nítorí pé èmi pa ọ̀nà Olúwa mọ́,
    èmi kò sì fi ìwà búburú yapa kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run mi.
23 Nítorí pé gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ ni ó wà níwájú mi;
    àti ní ti òfin rẹ̀, èmi kò sì yapa kúrò nínú wọn.
24 Èmi sì wà nínú ìwà títọ́ sí í,
    èmi sì pa ara mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi.
25 Olúwa sì san fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi,
    gẹ́gẹ́ bí ìwà mímọ́ mi níwájú rẹ̀.

26 “Fún aláàánú ni ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ni aláàánú,
    àti fún ẹni ìdúró ṣinṣin ní òdodo ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní ìdúró ṣinṣin ní òdodo.
27 Fún onínú funfun ni ìwọ fi ara rẹ hàn ní funfun;
    àti fún ẹni wíwọ́ ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní wíwọ́.
28 Àwọn ènìyàn tí ó wà nínú ìyà ni ìwọ ó sì gbàlà;
    ṣùgbọ́n ojú rẹ wà lára àwọn agbéraga, láti rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
29 Nítorí ìwọ ni ìmọ́lẹ̀ mi, Olúwa;
    Olúwa yóò sì sọ òkùnkùn mi di ìmọ́lẹ̀.
30 Bẹ́ẹ̀ ni nítorí nípa rẹ̀ ni èmi ti la àárín ogun kọjá;
    nípa Ọlọ́run mi èmi ti fo odi kan.

31 “Ọlọ́run yìí, pípé ni ọ̀nà rẹ̀;
    ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ti dánwò.
    Òun sì ni asà fún gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e.
32 Nítorí ta ni Ọlọ́run, bí kò ṣe Olúwa?
    Ta ni àpáta, bí kò ṣe Ọlọ́run wa.
33 Ọlọ́run alágbára ni ó fún mi ní agbára,
    ó sì sọ ọ̀nà mi di títọ́.
34 Ó ṣe ẹsẹ̀ mi bí ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín;
    ó sì mú mi dúró ní ibi gíga mi.
35 Ó kọ́ ọwọ́ mi ní ogun jíjà;
    tó bẹ́ẹ̀ tí apá mi fa ọrun idẹ.
36 Ìwọ sì ti fún mi ní asà
    ìgbàlà rẹ̀, ìrẹ̀lẹ̀ rẹ̀ sì ti sọ mí di ńlá.
37 Ìwọ sì sọ ìtẹ̀lẹ̀ di ńlá ní abẹ́ mi;
    tó bẹ́ẹ̀ tí ẹsẹ̀ mi kò fi yọ̀.

38 “Èmi ti lépa àwọn ọ̀tá mi, èmi sì ti run wọ́n,
    èmi kò pẹ̀yìndà títí èmi fi run wọ́n.
39 Èmi ti pa wọ́n run, èmi sì ti fọ́ wọn,
    wọn kò sì le dìde mọ́: wọ́n ṣubú lábẹ́ mi.
40 Ìwọ sì ti fi agbára dì mí ní àmùrè fún ìjà;
    àwọn tí ó ti dìde sí mi ni ìwọ sì ti tẹ̀ lórí ba fún mi.
41 Ìwọ sì mú àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà fún mi,
    èmi ó sì pa àwọn tí ó kórìíra mi run.
42 Wọ́n wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan láti gbà wọ́n;
    wọ́n wo Olúwa, ṣùgbọ́n kò dá àwọn lóhùn.
43 Nígbà náà ni èmi sì gún wọn wẹ́wẹ́ bí erùpẹ̀ ilẹ̀,
    èmi sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ bí ẹrẹ̀ ìta, èmi sì tẹ́ wọn gbọrọ.

44 “Ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìjà àwọn ènìyàn mi,
    ìwọ pa mi mọ́ ki èmi lè ṣe olórí àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè.
Àwọn ènìyàn tí èmi kò tí mọ̀ yóò máa sìn mí.
45     Àwọn àjèjì wá láti tẹríba fún mi;
    bí wọ́n bá ti gbúròó mi, wọ́n á sì gbọ́ tèmi.
46 Àyà yóò pá àwọn àlejò,
    wọ́n ó sì fi ìbẹ̀rù sá kúrò níbi kọ́lọ́fín wọn.

47 Olúwa ń bẹ́; olùbùkún sì ni àpáta mi!
    Gbígbéga sì ni Ọlọ́run àpáta ìgbàlà mi.
48 Ọlọ́run ni ẹni tí ń gbẹ̀san mi,
    àti ẹni tí ń rẹ àwọn ènìyàn sílẹ̀ lábẹ́ mi.
49     Àti ẹni tí ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.
Ìwọ sì gbé mi sókè ju àwọn tí ó kórìíra mi lọ;
    ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọkùnrin oníwà ipá.
50 (B)Nítorí náà èmi ó fi ọpẹ́ fún ọ, Olúwa,
    láàrín àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè: èmi ó sì kọrin sí orúkọ rẹ.

51 “Òun ni ilé ìṣọ́ ìgbàlà fún ọba rẹ̀;
    ó sì fi àánú hàn fún ẹni ààmì òróró rẹ̀,
    fún Dafidi, àti fún irú-ọmọ rẹ̀ títí láéláé.”

David’s Song of Praise(A)

22 David sang(B) to the Lord the words of this song when the Lord delivered him from the hand of all his enemies and from the hand of Saul. He said:

“The Lord is my rock,(C) my fortress(D) and my deliverer;(E)
    my God is my rock, in whom I take refuge,(F)
    my shield[a](G) and the horn[b](H) of my salvation.
He is my stronghold,(I) my refuge and my savior—
    from violent people you save me.

“I called to the Lord, who is worthy(J) of praise,
    and have been saved from my enemies.
The waves(K) of death swirled about me;
    the torrents of destruction overwhelmed me.
The cords of the grave(L) coiled around me;
    the snares of death confronted me.

“In my distress(M) I called(N) to the Lord;
    I called out to my God.
From his temple he heard my voice;
    my cry came to his ears.
The earth(O) trembled and quaked,(P)
    the foundations(Q) of the heavens[c] shook;
    they trembled because he was angry.
Smoke rose from his nostrils;
    consuming fire(R) came from his mouth,
    burning coals(S) blazed out of it.
10 He parted the heavens and came down;
    dark clouds(T) were under his feet.
11 He mounted the cherubim(U) and flew;
    he soared[d] on the wings of the wind.(V)
12 He made darkness(W) his canopy around him—
    the dark[e] rain clouds of the sky.
13 Out of the brightness of his presence
    bolts of lightning(X) blazed forth.
14 The Lord thundered(Y) from heaven;
    the voice of the Most High resounded.
15 He shot his arrows(Z) and scattered the enemy,
    with great bolts of lightning he routed them.
16 The valleys of the sea were exposed
    and the foundations of the earth laid bare
at the rebuke(AA) of the Lord,
    at the blast(AB) of breath from his nostrils.

17 “He reached down from on high(AC) and took hold of me;
    he drew(AD) me out of deep waters.
18 He rescued(AE) me from my powerful enemy,
    from my foes, who were too strong for me.
19 They confronted me in the day of my disaster,
    but the Lord was my support.(AF)
20 He brought me out into a spacious(AG) place;
    he rescued(AH) me because he delighted(AI) in me.(AJ)

21 “The Lord has dealt with me according to my righteousness;(AK)
    according to the cleanness(AL) of my hands(AM) he has rewarded me.
22 For I have kept(AN) the ways of the Lord;
    I am not guilty of turning from my God.
23 All his laws are before me;(AO)
    I have not turned(AP) away from his decrees.
24 I have been blameless(AQ) before him
    and have kept myself from sin.
25 The Lord has rewarded me according to my righteousness,(AR)
    according to my cleanness[f] in his sight.

26 “To the faithful you show yourself faithful,
    to the blameless you show yourself blameless,
27 to the pure(AS) you show yourself pure,
    but to the devious you show yourself shrewd.(AT)
28 You save the humble,(AU)
    but your eyes are on the haughty(AV) to bring them low.(AW)
29 You, Lord, are my lamp;(AX)
    the Lord turns my darkness into light.
30 With your help I can advance against a troop[g];
    with my God I can scale a wall.

31 “As for God, his way is perfect:(AY)
    The Lord’s word is flawless;(AZ)
    he shields(BA) all who take refuge in him.
32 For who is God besides the Lord?
    And who is the Rock(BB) except our God?(BC)
33 It is God who arms me with strength[h]
    and keeps my way secure.
34 He makes my feet like the feet of a deer;(BD)
    he causes me to stand on the heights.(BE)
35 He trains my hands(BF) for battle;
    my arms can bend a bow(BG) of bronze.
36 You make your saving help my shield;(BH)
    your help has made[i] me great.
37 You provide a broad path(BI) for my feet,
    so that my ankles do not give way.

38 “I pursued my enemies and crushed them;
    I did not turn back till they were destroyed.
39 I crushed(BJ) them completely, and they could not rise;
    they fell beneath my feet.
40 You armed me with strength for battle;
    you humbled my adversaries before me.(BK)
41 You made my enemies turn their backs(BL) in flight,
    and I destroyed my foes.
42 They cried for help,(BM) but there was no one to save them—(BN)
    to the Lord, but he did not answer.(BO)
43 I beat them as fine as the dust(BP) of the earth;
    I pounded and trampled(BQ) them like mud(BR) in the streets.

44 “You have delivered(BS) me from the attacks of the peoples;
    you have preserved(BT) me as the head of nations.
People(BU) I did not know now serve me,
45     foreigners cower(BV) before me;
    as soon as they hear of me, they obey me.(BW)
46 They all lose heart;
    they come trembling[j](BX) from their strongholds.

47 “The Lord lives! Praise be to my Rock!
    Exalted(BY) be my God, the Rock, my Savior!(BZ)
48 He is the God who avenges(CA) me,(CB)
    who puts the nations under me,
49     who sets me free from my enemies.(CC)
You exalted me(CD) above my foes;
    from a violent man you rescued me.
50 Therefore I will praise you, Lord, among the nations;
    I will sing the praises(CE) of your name.(CF)

51 “He gives his king great victories;(CG)
    he shows unfailing kindness to his anointed,(CH)
    to David(CI) and his descendants forever.”(CJ)

Footnotes

  1. 2 Samuel 22:3 Or sovereign
  2. 2 Samuel 22:3 Horn here symbolizes strength.
  3. 2 Samuel 22:8 Hebrew; Vulgate and Syriac (see also Psalm 18:7) mountains
  4. 2 Samuel 22:11 Many Hebrew manuscripts (see also Psalm 18:10); most Hebrew manuscripts appeared
  5. 2 Samuel 22:12 Septuagint (see also Psalm 18:11); Hebrew massed
  6. 2 Samuel 22:25 Hebrew; Septuagint and Vulgate (see also Psalm 18:24) to the cleanness of my hands
  7. 2 Samuel 22:30 Or can run through a barricade
  8. 2 Samuel 22:33 Dead Sea Scrolls, some Septuagint manuscripts, Vulgate and Syriac (see also Psalm 18:32); Masoretic Text who is my strong refuge
  9. 2 Samuel 22:36 Dead Sea Scrolls; Masoretic Text shield; / you stoop down to make
  10. 2 Samuel 22:46 Some Septuagint manuscripts and Vulgate (see also Psalm 18:45); Masoretic Text they arm themselves