Add parallel Print Page Options

Ìṣúra nínú ohun-èlò amọ̀

Nítorí náà, níwọ̀n bí ó ti jẹ́ pé nípa àánú Ọlọ́run ni a rí iṣẹ́ ìránṣẹ́ yìí gba, àárẹ̀ kò mú ọkàn wa rara; Ṣùgbọ́n àwa tí kọ gbogbo ohun ìkọ̀kọ̀ tí ó ní ìtìjú sílẹ̀, àwa kò rìn ní ẹ̀tàn, bẹ́ẹ̀ ni àwa kò fi ọwọ́ ẹ̀tàn mú ọ̀rọ̀ Ọlọ́run; ṣùgbọ́n nípa fífi òtítọ́ hàn, àwa ń fi ara wa le ẹ̀rí ọkàn olúkúlùkù ènìyàn lọ́wọ́ níwájú Ọlọ́run. Ṣùgbọ́n báyìí, bí Ìhìnrere wa bá sí fi ara sin, ó fi ara sin fún àwọn tí ó ń ṣègbé. (A)Nínú àwọn ẹni tí ọlọ́run ayé yìí ti sọ ọkàn àwọn aláìgbàgbọ́ dí afọ́jú, kí ìmọ́lẹ̀ ìhìnrere Kristi tí ó lógo, ẹni tí í ṣe àwòrán Ọlọ́run, má ṣe mọ́lẹ̀ nínú wọn. Nítorí àwa kò wàásù àwa tìkára wa, bí kò ṣe Kristi Jesu Olúwa; àwa tìkára wa sì jẹ́ ẹrú yín nítorí Jesu. (B)Nítorí Ọlọ́run ni ẹni tí ó wí pé, “Kí ìmọ́lẹ̀ ó tan láti inú òkùnkùn jáde,” òun ní ó ti ń tan mọ́lẹ̀ lọ́kàn wa, láti fún wa ní ìmọ́lẹ̀ ìmọ̀ ògo Ọlọ́run ní ojú Jesu Kristi.

Ṣùgbọ́n àwa ní ìṣúra yìí nínú ohun èlò amọ̀, kí ọláńlá agbára náà lè jẹ́ ti Ọlọ́run, kí ó má ṣe ti ọ̀dọ̀ wa wá. A ń pọ́n wa lójú níhà gbogbo, ṣùgbọ́n ara kò ni wá: a ń dààmú wa, ṣùgbọ́n a kò sọ ìrètí nù. A ń ṣe inúnibíni sí wa, ṣùgbọ́n a kò kọ̀ wá sílẹ̀; a ń rẹ̀ wá sílẹ̀ ṣùgbọ́n a kò pa wá run. 10 Nígbà gbogbo àwa ń ru ikú Jesu Olúwa kiri ni ará wa, kí a lè fi ìyè Jesu hàn pẹ̀lú lára wa. 11 Nítorí pé nígbà gbogbo ní a ń fi àwa tí ó wà láààyè fún ikú nítorí Jesu, kí a lè fi ìyè hàn nínú ara kíkú wa pẹ̀lú. 12 Bẹ́ẹ̀ ni ikú ń ṣiṣẹ́ nínú wa, ṣùgbọ́n ìyè ṣiṣẹ́ nínú yín.

13 (C)Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ́ pé, “Èmi gbàgbọ́, nítorí náà ni èmi ṣe sọ,” pẹ̀lú ẹ̀mí ìgbàgbọ́ kan náà, a tún gbàgbọ́ àti nítorí náà ni àwa sì ṣe ń sọ. 14 (D)Àwa mọ̀ pé, ẹni tí o jí Jesu Olúwa dìde yóò sì jí wa dìde pẹ̀lú nípa Jesu, yóò sì mú wa wà níwájú rẹ̀ pẹ̀lú yín 15 Nítorí tiyín ní gbogbo rẹ̀, ki ọ̀pẹ lè dí púpọ̀ fún ògo Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí oore-ọ̀fẹ́ ti ń gbòòrò sí i fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn.

16 Nítorí èyí ni àárẹ̀ kò ṣe mú wa; ṣùgbọ́n bí ọkùnrin ti òde wa bá ń parun, síbẹ̀ ọkùnrin tí inú wa ń di tuntun lójoojúmọ́. 17 Nítorí ìpọ́njú díẹ̀ yìí ń pèsè ògo tí ó ní ìwọ̀n ayérayé tí ó pọ̀ rékọjá sílẹ̀ fún wa. 18 Níwọ́n bí kò ti wo ohun tí a ń rí, bí kò ṣé ohun tí a kò rí; nítorí ohun tí a ń rí ni ti ìgbà ìsinsin yìí; ṣùgbọ́n ohun tí a kò rí ni ti ayérayé.

Present Weakness and Resurrection Life

Therefore, since through God’s mercy(A) we have this ministry, we do not lose heart.(B) Rather, we have renounced secret and shameful ways;(C) we do not use deception, nor do we distort the word of God.(D) On the contrary, by setting forth the truth plainly we commend ourselves to everyone’s conscience(E) in the sight of God. And even if our gospel(F) is veiled,(G) it is veiled to those who are perishing.(H) The god(I) of this age(J) has blinded(K) the minds of unbelievers, so that they cannot see the light of the gospel that displays the glory of Christ,(L) who is the image of God.(M) For what we preach is not ourselves,(N) but Jesus Christ as Lord,(O) and ourselves as your servants(P) for Jesus’ sake. For God, who said, “Let light shine out of darkness,”[a](Q) made his light shine in our hearts(R) to give us the light of the knowledge of God’s glory displayed in the face of Christ.(S)

But we have this treasure in jars of clay(T) to show that this all-surpassing power is from God(U) and not from us. We are hard pressed on every side,(V) but not crushed; perplexed,(W) but not in despair; persecuted,(X) but not abandoned;(Y) struck down, but not destroyed.(Z) 10 We always carry around in our body the death of Jesus,(AA) so that the life of Jesus may also be revealed in our body.(AB) 11 For we who are alive are always being given over to death for Jesus’ sake,(AC) so that his life may also be revealed in our mortal body. 12 So then, death is at work in us, but life is at work in you.(AD)

13 It is written: “I believed; therefore I have spoken.”[b](AE) Since we have that same spirit of[c] faith,(AF) we also believe and therefore speak, 14 because we know that the one who raised the Lord Jesus from the dead(AG) will also raise us with Jesus(AH) and present us with you to himself.(AI) 15 All this is for your benefit, so that the grace that is reaching more and more people may cause thanksgiving(AJ) to overflow to the glory of God.

16 Therefore we do not lose heart.(AK) Though outwardly we are wasting away, yet inwardly(AL) we are being renewed(AM) day by day. 17 For our light and momentary troubles are achieving for us an eternal glory that far outweighs them all.(AN) 18 So we fix our eyes not on what is seen, but on what is unseen,(AO) since what is seen is temporary, but what is unseen is eternal.

Footnotes

  1. 2 Corinthians 4:6 Gen. 1:3
  2. 2 Corinthians 4:13 Psalm 116:10 (see Septuagint)
  3. 2 Corinthians 4:13 Or Spirit-given