Add parallel Print Page Options

Ẹ dán àwọn ẹ̀mí wò

Olùfẹ́, ẹ má ṣe gba gbogbo ẹ̀mí gbọ́, ṣùgbọ́n ẹ dán àwọn ẹ̀mí wò bí wọn ba ń ṣe tí Ọlọ́run: nítorí àwọn wòlíì èké púpọ̀ tí jáde lọ sínú ayé. Èyí ni ẹ ó fi mọ Ẹ̀mí Ọlọ́run: gbogbo ẹ̀mí tí ó ba jẹ́wọ́ pé, Jesu Kristi wá nínú ara, ti Ọlọ́run ni: (A)Gbogbo ẹ̀mí tí kò si jẹ́wọ́ pé Jesu Kristi wà nínú ara, kì í ṣe tí Ọlọ́run: èyí sì ni ẹ̀mí aṣòdì sí Kristi náà, tí ẹ̀yin ti gbọ́ pé ó ń bọ̀, àti nísinsin yìí ó sì tí de sínú ayé.

Ẹ̀yin ọmọ mi, ti Ọlọ́run ni yín, ẹ̀yin sì tí ṣẹ́gun wọn: nítorí ẹni tí ń bẹ nínú yin tóbi jú ẹni tí ń bẹ nínú ayé lọ. (B)Tí ayé ni wọ́n, nítorí náà ni wọn ṣe ń sọ̀rọ̀ bí ẹni ti ayé, ayé sì ń gbọ́ tí wọn. (C)Ti Ọlọ́run ni àwa: ẹni tí ó bá mọ Ọlọ́run, ó ń gbọ́ tiwa; ẹni tí kì í ṣe ti Ọlọ́run kò ni gbọ́ ti wa. Nípa èyí ni àwa mọ ẹ̀mí òtítọ́, àti ẹ̀mí èké.

Ìfẹ́ Ọlọ́run àti ti àwa

(D)Olùfẹ́, ẹ jẹ́ kí a fẹ́ràn ara wa: nítorí ìfẹ́ ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá; àti gbogbo ẹni tí ó bá ní ìfẹ́, a bí i nípa ti Ọlọ́run, ó sì mọ Ọlọ́run. Ẹni tí kò bá ní ìfẹ́ kò mọ Ọlọ́run: nítorí pé ìfẹ́ ni Ọlọ́run. (E)Nípa èyí ni a gbé fi ìfẹ́ Ọlọ́run hàn nínú wa, nítorí tí Ọlọ́run rán ọmọ bíbí rẹ̀ nìkan ṣoṣo sì ayé, kí àwa lè yè nípasẹ̀ rẹ̀. 10 (F)Nínú èyí ni ìfẹ́ wà, kì í ṣe pé àwa fẹ́ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n òun fẹ́ wá, ó sì rán Ọmọ rẹ̀ láti jẹ́ ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ wa. 11 Olùfẹ́, bí Ọlọ́run bá fẹ́ wa báyìí, ó yẹ kí a fẹ́ràn ara wa pẹ̀lú. 12 (G)Ẹnikẹ́ni kò ri Ọlọ́run nígbà kan rí. Bí àwa bá fẹ́ràn ara wa, Ọlọ́run ń gbé inú wa, a sì mú ìfẹ́ rẹ̀ pé nínú wa.

13 (H)Nípa èyí ni àwa mọ̀ pé àwa ń gbé inú rẹ̀, àti Òun nínú wa, nítorí tí ó ti fi Ẹ̀mí rẹ̀ fún wa. 14 (I)Àwa tí rí, a sì jẹ́rìí pé Baba rán Ọmọ rẹ̀ láti jẹ́ Olùgbàlà fún aráyé. 15 Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́wọ́ pé Jesu Ọmọ Ọlọ́run ni, Ọlọ́run ń gbé inú rẹ̀, àti òun nínú Ọlọ́run. 16 Báyìí ni àwa mọ̀, tí a sì gba ìfẹ́ tí Ọlọ́run ní sí wa gbọ́.

Ìfẹ́ ni Ọlọ́run; ẹni tí ó bá sì ń gbé inú ìfẹ́, ó ń gbé inú Ọlọ́run, àti Ọlọ́run nínú rẹ̀. 17 (J)Nínú èyí ni a mú ìfẹ́ tí ó wà nínú wa pé, kí àwa bà á lè ni ìgboyà ní ọjọ́ ìdájọ́: nítorí pé bí òun tí rí, bẹ́ẹ̀ ni àwa sì rí ni ayé yìí. 18 Ìbẹ̀rù kò sí nínú ìfẹ́; ṣùgbọ́n ìfẹ́ tí ó pé ń lé ìbẹ̀rù jáde; nítorí tí ìbẹ̀rù ni ìyà nínú. Ẹni tí ó bẹ̀rù kò pé nínú ìfẹ́.

19 (K)Àwa fẹ́ràn rẹ̀ nítorí òun ni ó kọ́ fẹ́ràn wa. 20 (L)Bí ẹnikẹ́ni bá wí pé, “Èmi fẹ́ràn Ọlọ́run,” tí ó sì kórìíra arákùnrin rẹ̀, èké ni: nítorí ẹni tí kò fẹ́ràn arákùnrin rẹ̀ tí ó rí, báwo ni yóò tí ṣe lè fẹ́ràn Ọlọ́run tí òun kò rí? 21 Òfin yìí ni àwa sì rí gbà láti ọwọ́ rẹ̀ wá, pé ẹni tí ó bá fẹ́ràn Ọlọ́run kí ó fẹ́ràn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú.

On Denying the Incarnation

Dear friends,(A) do not believe every spirit,(B) but test the spirits to see whether they are from God, because many false prophets have gone out into the world.(C) This is how you can recognize the Spirit of God: Every spirit that acknowledges that Jesus Christ has come in the flesh(D) is from God,(E) but every spirit that does not acknowledge Jesus is not from God. This is the spirit of the antichrist,(F) which you have heard is coming and even now is already in the world.(G)

You, dear children,(H) are from God and have overcome them,(I) because the one who is in you(J) is greater than the one who is in the world.(K) They are from the world(L) and therefore speak from the viewpoint of the world, and the world listens to them. We are from God, and whoever knows God listens to us; but whoever is not from God does not listen to us.(M) This is how we recognize the Spirit[a] of truth(N) and the spirit of falsehood.(O)

God’s Love and Ours

Dear friends, let us love one another,(P) for love comes from God. Everyone who loves has been born of God(Q) and knows God.(R) Whoever does not love does not know God, because God is love.(S) This is how God showed his love among us: He sent his one and only Son(T) into the world that we might live through him.(U) 10 This is love: not that we loved God, but that he loved us(V) and sent his Son as an atoning sacrifice for our sins.(W) 11 Dear friends,(X) since God so loved us,(Y) we also ought to love one another.(Z) 12 No one has ever seen God;(AA) but if we love one another, God lives in us and his love is made complete in us.(AB)

13 This is how we know(AC) that we live in him and he in us: He has given us of his Spirit.(AD) 14 And we have seen and testify(AE) that the Father has sent his Son to be the Savior of the world.(AF) 15 If anyone acknowledges that Jesus is the Son of God,(AG) God lives in them and they in God.(AH) 16 And so we know and rely on the love God has for us.

God is love.(AI) Whoever lives in love lives in God, and God in them.(AJ) 17 This is how love is made complete(AK) among us so that we will have confidence(AL) on the day of judgment:(AM) In this world we are like Jesus. 18 There is no fear in love. But perfect love drives out fear,(AN) because fear has to do with punishment. The one who fears is not made perfect in love.

19 We love because he first loved us.(AO) 20 Whoever claims to love God yet hates a brother or sister(AP) is a liar.(AQ) For whoever does not love their brother and sister, whom they have seen,(AR) cannot love God, whom they have not seen.(AS) 21 And he has given us this command:(AT) Anyone who loves God must also love their brother and sister.(AU)

Footnotes

  1. 1 John 4:6 Or spirit