Add parallel Print Page Options

Báwo ni Olúwa ṣe bo ọmọbìnrin Sioni
    pẹ̀lú àwọsánmọ̀ ìbínú rẹ̀!
Ó sọ ògo Israẹli kalẹ̀
    Láti ọ̀run sí ayé;
kò rántí àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀
    ní ọjọ́ ìbínú rẹ̀.

Láìní àánú ni Olúwa gbé
    ibùgbé Jakọbu mì;
nínú ìrunú rẹ̀, ni ó wó
    ibi gíga ọmọbìnrin Juda lulẹ̀.
Ó ti mú ìjọba àti àwọn ọmọ-aládé ọkùnrin
    lọ sínú ilẹ̀ ní àìlọ́wọ̀.

Ní ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó ké
    gbogbo ìwo Israẹli.
Ó ti mú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ kúrò
    nígbà tí àwọn ọ̀tá dé.
Ó run ní Jakọbu bí ọ̀wọ́-iná
    ní àgọ́ àwọn ọmọbìnrin Sioni.

Ó na ọfà rẹ̀ bí ọ̀tá;
    ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ sì múra
Bí ti ọ̀tá tí ó ti parun
    ó tú ìbínú rẹ̀ jáde bí iná
sórí àgọ́ ọmọbìnrin Sioni.

Olúwa dàbí ọ̀tá;
    ó gbé Israẹli mì.
Ó ti gbé gbogbo ààfin rẹ̀ mì
    ó pa ibi gíga rẹ̀ run.
Ó sọ ìmí ẹ̀dùn àti ìbànújẹ́ di púpọ̀
    fún àwọn ọmọbìnrin Juda.

Ó mú ìparun bá ibi mímọ́,
    ó pa ibi ìpàdé rẹ̀ run.
Olúwa ti mú Sioni gbàgbé
    àjọ̀dún tí a yàn àti ọ̀sẹ̀ tí ó yàn;
nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó run
    ọba àti olórí àlùfáà.

Olúwa ti kọ̀ pẹpẹ rẹ̀ sílẹ̀
    ó sì ti kọ̀ ibi mímọ́ rẹ̀.
Ó sì fi lé ọ̀tá lọ́wọ́
    àwọn odi ààfin rẹ̀;
wọ́n sì kígbe ní ilé Olúwa
    gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ àpèjẹ tí a yàn.

Olúwa pinnu láti fa
    ògiri tí ó yí ọmọbìnrin Sioni ya.
Ó gbé wọn sórí òṣùwọ̀n,
    kò sì fa ọwọ́ rẹ̀ padà kúrò nínú ìparun wọn.
Ó mú kí ilé ìṣọ́ àti odi rẹ̀ ṣọ̀fọ̀
    wọ́n ṣòfò papọ̀.

Ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ ti wọ inú ilẹ̀;
    òpó rẹ̀ ni ó wó tí ó sì ti bàjẹ́.
Ọba àti ọmọ ọbakùnrin rẹ̀ wà ní ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
    kò sí òfin mọ́,
àwọn wòlíì rẹ̀ kò rí
    ìran láti ọ̀dọ̀ Olúwa mọ́.

10 Àwọn àgbàgbà ọmọbìnrin Sioni
    jókòó sílẹ̀ ní ìdákẹ́rọ́rọ́;
wọ́n da eruku sí orí wọn
    wọ́n sì wọ aṣọ àkísà.
Àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Jerusalẹmu
    ti tẹrí wọn ba sí ilẹ̀.

11 Ojú mi kọ̀ láti sọkún,
    mo ń jẹ ìrora nínú mi,
mo tú ọkàn mi jáde sí ilẹ̀
    nítorí a pa àwọn ènìyàn mí run,
nítorí àwọn ọmọdé àti ọmọ ọwọ́ ń kú
    ní òpópó ìlú.

12 Wọ́n wí fún àwọn ìyá wọn,
    “Níbo ni ọkà àti wáìnì wà?” Wò ó
bí wọ́n ṣe ń kú lọ bí àwọn ọkùnrin tí a ṣe léṣe
    ní àwọn òpópónà ìlú,
bí ayé wọn ṣe ń ṣòfò
    láti ọwọ́ ìyá wọn.

13 Kí ni mo le sọ fún ọ?
    Pẹ̀lú kí ni mo lè fi ọ́ wé,
    Ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu?
Kí sì ni mo lè fi ọ́ wé,
    kí n lè tù ọ́ nínú,
    Ìwọ wúńdíá obìnrin Sioni?
Ọgbẹ́ rẹ jì bí Òkun.
    Ta ni yóò wò ọ́ sàn?

14 Ìran àwọn wòlíì rẹ
    jẹ́ kìkì ẹ̀tàn láìní ìwọ̀n;
wọn kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ hàn
    tí yóò mú ìgbèkùn kúrò fún ọ.
Àwọn òrìṣà tí wọ́n fún ọ
    jẹ́ èké àti ìmúniṣìnà.

15 Àwọn tí ó gba ọ̀nà ọ̀dọ̀ rẹ
    pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí;
wọ́n kẹ́gàn wọ́n ju orí wọn
    sí ọmọbìnrin Jerusalẹmu:
“Èyí ha ni ìlú tí à ń pè ní
    àṣepé ẹwà,
    ìdùnnú gbogbo ayé?”

16 Gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ la ẹnu wọn
    gbòòrò sí ọ;
wọ́n kẹ́gàn, wọ́n sì payínkeke
    wọ́n wí pé, “A ti gbé e mì tán.
Èyí ni ọjọ́ tí a ti ń retí;
    tí a sì wá láti rí.”

17 Olúwa ti ṣe ohun tí ó pinnu;
    ó ti mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ,
    tí ó sì pàṣẹ ní ọjọ́ pípẹ́.
Ó ti ṣí ọ ní ipò láì láàánú,
    ó fún ọ̀tá ní ìṣẹ́gun lórí rẹ,
    ó ti gbé ìwo àwọn ọ̀tá rẹ̀ ga.

18 Ọkàn àwọn ènìyàn
    kígbe jáde sí Olúwa.
Odi ọmọbìnrin Sioni,
    jẹ́ kí ẹkún rẹ̀ sàn bí odò
    ní ọ̀sán àti òru;
má ṣe fi ara rẹ fún ìtura,
    ojú rẹ fún ìsinmi.

19 Dìde, kígbe sókè ní àṣálẹ́,
    bí ìṣọ́ òru ti bẹ̀rẹ̀
tú ọkàn rẹ̀ jáde bí omi
    níwájú Olúwa.
Gbé ọwọ́ yín sókè sí i
    nítorí ẹ̀mí àwọn èwe rẹ̀
tí ó ń kú lọ nítorí ebi
    ní gbogbo oríta òpópó.

20 “Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó:
    Ta ni ìwọ ti fìyà jẹ bí èyí
Ǹjẹ́ àwọn obìnrin yóò ha jẹ ọmọ wọn,
    àwọn ọmọ tí wọn ń ṣe ìtọ́jú fún?
Ǹjẹ́ kí a pa olórí àlùfáà àti àwọn wòlíì
    ní ibi mímọ́ Olúwa?

21 “Ọmọdé àti àgbà ń sùn papọ̀
    sínú eruku àwọn òpópó;
àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi
    ti ṣègbé nípa idà.
Ìwọ pa wọ́n run ní ọjọ́ ìbínú rẹ;
    Ìwọ pa wọ́n láìní àánú.

22 “Bí ó ti ṣe ní ọjọ́ àsè,
    bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe fi ẹ̀rù sí ẹ̀gbẹ́ mi.
Ní ọjọ́ ìbínú Olúwa
    kò sí ẹni tí ó sálà tí ó sì yè;
àwọn tí mo ti tọ́jú tí mo sì fẹ́ràn,
    ni ọ̀tá mi parun.”

[a]How the Lord has covered Daughter Zion
    with the cloud of his anger[b]!(A)
He has hurled down the splendor of Israel
    from heaven to earth;
he has not remembered his footstool(B)
    in the day of his anger.(C)

Without pity(D) the Lord has swallowed(E) up
    all the dwellings of Jacob;
in his wrath he has torn down
    the strongholds(F) of Daughter Judah.
He has brought her kingdom and its princes
    down to the ground(G) in dishonor.

In fierce anger he has cut off
    every horn[c][d](H) of Israel.
He has withdrawn his right hand(I)
    at the approach of the enemy.
He has burned in Jacob like a flaming fire
    that consumes everything around it.(J)

Like an enemy he has strung his bow;(K)
    his right hand is ready.
Like a foe he has slain
    all who were pleasing to the eye;(L)
he has poured out his wrath(M) like fire(N)
    on the tent(O) of Daughter Zion.

The Lord is like an enemy;(P)
    he has swallowed up Israel.
He has swallowed up all her palaces
    and destroyed her strongholds.(Q)
He has multiplied mourning and lamentation(R)
    for Daughter Judah.(S)

He has laid waste his dwelling like a garden;
    he has destroyed(T) his place of meeting.(U)
The Lord has made Zion forget
    her appointed festivals and her Sabbaths;(V)
in his fierce anger he has spurned
    both king and priest.(W)

The Lord has rejected his altar
    and abandoned his sanctuary.(X)
He has given the walls of her palaces(Y)
    into the hands of the enemy;
they have raised a shout in the house of the Lord
    as on the day of an appointed festival.(Z)

The Lord determined to tear down
    the wall around Daughter Zion.(AA)
He stretched out a measuring line(AB)
    and did not withhold his hand from destroying.
He made ramparts(AC) and walls lament;
    together they wasted away.(AD)

Her gates(AE) have sunk into the ground;
    their bars(AF) he has broken and destroyed.
Her king and her princes are exiled(AG) among the nations,
    the law(AH) is no more,
and her prophets(AI) no longer find
    visions(AJ) from the Lord.

10 The elders of Daughter Zion
    sit on the ground in silence;(AK)
they have sprinkled dust(AL) on their heads(AM)
    and put on sackcloth.(AN)
The young women of Jerusalem
    have bowed their heads to the ground.(AO)

11 My eyes fail from weeping,(AP)
    I am in torment within(AQ);
my heart(AR) is poured out(AS) on the ground
    because my people are destroyed,(AT)
because children and infants faint(AU)
    in the streets of the city.

12 They say to their mothers,
    “Where is bread and wine?”(AV)
as they faint like the wounded
    in the streets of the city,
as their lives ebb away(AW)
    in their mothers’ arms.(AX)

13 What can I say for you?(AY)
    With what can I compare you,
    Daughter(AZ) Jerusalem?
To what can I liken you,
    that I may comfort you,
    Virgin Daughter Zion?(BA)
Your wound is as deep as the sea.(BB)
    Who can heal you?

14 The visions of your prophets
    were false(BC) and worthless;
they did not expose your sin
    to ward off your captivity.(BD)
The prophecies they gave you
    were false and misleading.(BE)

15 All who pass your way
    clap their hands at you;(BF)
they scoff(BG) and shake their heads(BH)
    at Daughter Jerusalem:(BI)
“Is this the city that was called
    the perfection of beauty,(BJ)
    the joy of the whole earth?”(BK)

16 All your enemies open their mouths
    wide against you;(BL)
they scoff and gnash their teeth(BM)
    and say, “We have swallowed her up.(BN)
This is the day we have waited for;
    we have lived to see it.”(BO)

17 The Lord has done what he planned;
    he has fulfilled(BP) his word,
    which he decreed long ago.(BQ)
He has overthrown you without pity,(BR)
    he has let the enemy gloat over you,(BS)
    he has exalted the horn[e] of your foes.(BT)

18 The hearts of the people
    cry out to the Lord.(BU)
You walls of Daughter Zion,(BV)
    let your tears(BW) flow like a river
    day and night;(BX)
give yourself no relief,
    your eyes no rest.(BY)

19 Arise, cry out in the night,
    as the watches of the night begin;
pour out your heart(BZ) like water
    in the presence of the Lord.(CA)
Lift up your hands(CB) to him
    for the lives of your children,
who faint(CC) from hunger
    at every street corner.

20 “Look, Lord, and consider:
    Whom have you ever treated like this?
Should women eat their offspring,(CD)
    the children they have cared for?(CE)
Should priest and prophet be killed(CF)
    in the sanctuary of the Lord?(CG)

21 “Young and old lie together
    in the dust of the streets;
my young men and young women
    have fallen by the sword.(CH)
You have slain them in the day of your anger;
    you have slaughtered them without pity.(CI)

22 “As you summon to a feast day,
    so you summoned against me terrors(CJ) on every side.
In the day of the Lord’s anger
    no one escaped(CK) or survived;
those I cared for and reared(CL)
    my enemy has destroyed.”

Footnotes

  1. Lamentations 2:1 This chapter is an acrostic poem, the verses of which begin with the successive letters of the Hebrew alphabet.
  2. Lamentations 2:1 Or How the Lord in his anger / has treated Daughter Zion with contempt
  3. Lamentations 2:3 Or off / all the strength; or every king
  4. Lamentations 2:3 Horn here symbolizes strength.
  5. Lamentations 2:17 Horn here symbolizes strength.