Òwe 31
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
31 Àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ ti Lemueli ọba,
ọ̀rọ̀ ẹ̀kọ́ tí ìyá rẹ̀ kọ́ ọ.
2 “Gbọ́ ìwọ ọmọ mi, gbọ́ ìwọ ọmọ inú mi!
Gbọ́ ìwọ ọmọ ẹ̀jẹ́ mi.
3 Má ṣe lo agbára rẹ lórí obìnrin,
okun rẹ lórí àwọn tí ó pa àwọn ọba run.
4 “Kì í ṣe fún àwọn ọba, ìwọ Lemueli
kì í ṣe fún ọba láti mu ọtí wáìnì
kì í ṣe fún alákòóso láti máa wá ọtí líle
5 Kí wọn má ba à mu ọtí yó kí wọn sì gbàgbé ohun tí òfin wí
kí wọn sì fi ẹ̀tọ́ àwọn tí ara ń ni dù wọ́n
6 Fi ọtí líle fún àwọn tí ń ṣègbé
wáìnì fún àwọn tí ó wà nínú ìrora;
7 Jẹ́ kí wọn mu ọtí kí wọn sì gbàgbé òsì wọn
kí wọn má sì rántí òsì wọn mọ́.
8 “Sọ̀rọ̀ lórúkọ àwọn tí kò le sọ̀rọ̀ fúnrawọn
fún ẹ̀tọ́ àwọn ẹni tí ń parun
9 Sọ̀rọ̀ kí o sì ṣe ìdájọ́ àìṣègbè
jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà àti aláìní.”
10 Ta ni ó le rí aya oníwà rere?
Ó níye lórí ju iyùn lọ
11 Ọkọ rẹ̀ ní ìgbẹ́kẹ̀lé púpọ̀ nínú rẹ̀
kò sì ṣí ìwà rere tí kò pé lọ́wọ́ rẹ̀.
12 Ire ní ó ń ṣe fún un, kì í ṣe ibi
ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
13 Ó sa aṣọ irun àgùntàn olówùú àti ọ̀gbọ̀
Ó sì ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìyárí.
14 Ó dàbí ọkọ̀ ojú omi tí àwọn oníṣòwò;
ó ń gbé oúnjẹ rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn
15 Ó dìde nígbà tí òkùnkùn sì kùn;
ó ṣe oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀
àti ìpín oúnjẹ fún àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀.
16 Ó kíyèsi oko kan, ó sì rà á;
nínú ohun tí ó ń wọlé fún un ó gbin ọgbà àjàrà rẹ̀
17 Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ tagbára tagbára
apá rẹ̀ le koko fún iṣẹ́
18 Ó rí i pé òwò òun pé
fìtílà rẹ̀ kì í sì í kú ní òru
19 Ní ọwọ́ rẹ̀, ó di kẹ̀kẹ́ òwú mú
ó sì na ọwọ́ rẹ̀ di ìrànwú mú
20 O la ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn tálákà
ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn aláìní.
21 Nígbà tí òjò-dídì rọ̀, kò bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀
nítorí gbogbo wọn ni ó wọ aṣọ tí ó nípọn.
22 Ó ṣe aṣọ títẹ́ fún ibùsùn rẹ̀;
ẹ̀wù dáradára àti elése àlùkò ni aṣọ rẹ̀
23 A bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀ ní ẹnu ibodè ìlú
níbi tí ó ń jókòó láàrín àwọn àgbàgbà ìlú
24 Ó ń ṣe àwọn aṣọ dáradára ó sì ń tà wọ́n
ó sì ń kó ọjà fún àwọn oníṣòwò
25 Agbára àti ọlá ni ó wò ọ́ láṣọ
ó le fi ọjọ́ iwájú rẹ́rìn-ín.
26 A sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọgbọ́n
ìkọ́ni òtítọ́ sì ń bẹ létè e rẹ̀
27 Ó ń bojútó gbogbo ètò ilé rẹ̀
kì í sì í jẹ oúnjẹ ìmẹ́lẹ́
28 Àwọn ọmọ rẹ̀ dìde wọ́n sì pè é ní alábùkún
ọkọ rẹ̀ pẹ̀lú ń gbóríyìn fún un
29 “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ obìnrin ní ń ṣe nǹkan ọlọ́lá
ṣùgbọ́n ìwọ ju gbogbo wọn lọ”
30 Ojú dáradára a máa tan ni, ẹwà sì jẹ́ asán
nítorí obìnrin tí ó bẹ̀rù Olúwa yẹ kí ó gba oríyìn
31 Sì fún un ní èrè tí ó tọ́ sí i
kí o sì jẹ́ kí iṣẹ́ rẹ̀ fún un ní ìyìn ní ẹnu ibodè ìlú.
Proverbs 31
New International Version
Sayings of King Lemuel
31 The sayings(A) of King Lemuel—an inspired utterance his mother taught him.
2 Listen, my son! Listen, son of my womb!
Listen, my son, the answer to my prayers!(B)
3 Do not spend your strength[a] on women,
your vigor on those who ruin kings.(C)
4 It is not for kings, Lemuel—
it is not for kings to drink wine,(D)
not for rulers to crave beer,
5 lest they drink(E) and forget what has been decreed,(F)
and deprive all the oppressed of their rights.
6 Let beer be for those who are perishing,
wine(G) for those who are in anguish!
7 Let them drink(H) and forget their poverty
and remember their misery no more.
8 Speak(I) up for those who cannot speak for themselves,
for the rights of all who are destitute.
9 Speak up and judge fairly;
defend the rights of the poor and needy.(J)
Epilogue: The Wife of Noble Character
10 [b]A wife of noble character(K) who can find?(L)
She is worth far more than rubies.
11 Her husband(M) has full confidence in her
and lacks nothing of value.(N)
12 She brings him good, not harm,
all the days of her life.
13 She selects wool and flax
and works with eager hands.(O)
14 She is like the merchant ships,
bringing her food from afar.
15 She gets up while it is still night;
she provides food for her family
and portions for her female servants.
16 She considers a field and buys it;
out of her earnings she plants a vineyard.
17 She sets about her work vigorously;
her arms are strong for her tasks.
18 She sees that her trading is profitable,
and her lamp does not go out at night.
19 In her hand she holds the distaff
and grasps the spindle with her fingers.
20 She opens her arms to the poor
and extends her hands to the needy.(P)
21 When it snows, she has no fear for her household;
for all of them are clothed in scarlet.
22 She makes coverings for her bed;
she is clothed in fine linen and purple.
23 Her husband is respected at the city gate,
where he takes his seat among the elders(Q) of the land.
24 She makes linen garments and sells them,
and supplies the merchants with sashes.
25 She is clothed with strength and dignity;
she can laugh at the days to come.
26 She speaks with wisdom,
and faithful instruction is on her tongue.(R)
27 She watches over the affairs of her household
and does not eat the bread of idleness.
28 Her children arise and call her blessed;
her husband also, and he praises her:
29 “Many women do noble things,
but you surpass them all.”
30 Charm is deceptive, and beauty is fleeting;
but a woman who fears the Lord is to be praised.
31 Honor her for all that her hands have done,
and let her works bring her praise(S) at the city gate.
Footnotes
- Proverbs 31:3 Or wealth
- Proverbs 31:10 Verses 10-31 are an acrostic poem, the verses of which begin with the successive letters of the Hebrew alphabet.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.