Add parallel Print Page Options

20 Ẹlẹ́yà ni ọtí wáìnì, aláriwo sì ní ọtí líle
    ẹnikẹ́ni tí ó bá fi tànjẹ kò gbọ́n.

Ìbẹ̀rù ọba dàbí kíké e kìnnìún;
    ẹnikẹ́ni tí ó bá mú un bínú ba ayé ara rẹ̀ jẹ́.

Iyì ni ó jẹ́ fún ènìyàn láti sá fún ìjà,
    ṣùgbọ́n gbogbo aláìgbọ́n a máa tètè wá ìjà.

Ọ̀lẹ kì í ṣiṣẹ́ oko nígbà tí ó yẹ,
    nítorí náà ní àsìkò ìkórè, yóò wá kò sì ní rì nǹkan.

Ète ọkàn ènìyàn dàbí omi jíjìn;
    ṣùgbọ́n ènìyàn olóye á wá wọn jáde.

Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni wọ́n máa ń sọ pe àwọn ní ìfẹ́ àìṣẹ̀tàn,
    ṣùgbọ́n kò rọrùn láti rí ènìyàn olóòtítọ́.

Olódodo ènìyàn a máa gbé ìgbé ayé àìlábùkù
    ìbùkún ni fún àwọn ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.

Nígbà tí ọba bá jókòó sórí ìtẹ́ rẹ̀ láti ṣe ìdájọ́
    yóò fẹ́ gbogbo ibi dànù pẹ̀lú ojú rẹ̀.

Ta ni ó le è wí pé, “Mo ti ṣe ọkàn mi ní mímọ́,
    mo mọ́, n kò sì lẹ́ṣẹ̀”?

10 Ìwọ̀n èké àti òṣùwọ̀n ìrẹ́jẹ
    Olúwa kórìíra méjèèjì.

11 Kódà a mọ ọmọdé nípa iṣẹ́ rẹ̀
    nípa pe bóyá iṣẹ́ rẹ mọ́ tàbí pé ó tọ̀nà.

12 Etí tí ó ń gbọ́ àti ojú tí ó ń ríran
    Olúwa ni ó dá méjèèjì.

13 Má ṣe fẹ́ràn oorun, àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ yóò di tálákà.
    Ma ṣe sùn ìwọ yóò sì ní oúnjẹ láti tún fi tọrọ.

14 “Kò dára, kò dára” ní ẹni tó ra ọjà máa ń wí
    nígbà tí ó bá kúrò níbẹ̀ tán,
    yóò máa yangàn bí òun tí ṣe rí rà sí.

15 Wúrà wà, iyùn sì wà rẹpẹtẹ
    ṣùgbọ́n, ahọ́n tí ń sọ ìmọ̀ gan an ni ọ̀ṣọ́ iyebíye.

16 Gba abọ́ ẹni tí ó ṣe onídùúró fún àlejò;
    mú un lọ́wọ́ bí ìbúra bí ó bá ṣe é fún obìnrin onírìnkurìn.

17 Oúnjẹ tí a fi ọ̀nà èrú rí máa ń dùn lẹ́nu ènìyàn
    ṣùgbọ́n, a yọrí sí ibi ẹnu tí ó kún fún erùpẹ̀.

18 Pa ètè rẹ mọ́ nípa wíwá ìmọ̀ràn
    bí o bá ń jagun, gba ìtọ́sọ́nà.

19 Olófòófó a máa tú àṣírí
    nítorí náà yẹra fún ènìyàn tí ń rojọ́ púpọ̀.

20 Bí ènìyàn kan bá ṣépè fún baba tàbí ìyá rẹ̀,
    ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ni a ó pa kú nínú òkùnkùn biribiri.

21 Ogún tí a kójọ kíákíá ní ìbẹ̀rẹ̀
    kì yóò ní ìbùkún ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín.

22 Má ṣe wí pé, “N ó ṣẹ̀san àṣìṣe rẹ yìí fún ọ”
    Dúró de Olúwa yóò sì gbà ọ́ là.

23 Olúwa kórìíra òdínwọ̀n èké.
    Òṣùwọ̀n ìrẹ́jẹ kò sì tẹ́ ẹ lọ́rùn.

24 Olúwa ni ó ń ṣe olùdarí ìgbésẹ̀ ènìyàn
    Báwo wá ni òye gbogbo ọ̀nà ènìyàn ṣe le yé ni?

25 Ìdẹ̀kùn ni fún ènìyàn láti ṣe ìlérí kíákíá
    nígbà tí ó bá sì yá kí ó máa ro ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wò.

26 Ọlọ́gbọ́n ọba tú ènìyàn búburú ká;
    Ó sì fi òòlọ ìpakà lọ̀ wọ́n.

27 Àtùpà Olúwa ń ṣe àwárí ẹ̀mí ènìyàn
    a máa ṣàwárí ibi ìkọ̀kọ̀ inú.

28 Ìfẹ́ àti òdodo pa ọba mọ́,
    nípa ìfẹ́, ìtẹ́ rẹ̀ wà láìléwu.

29 Ògo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ni agbára wọn,
    ewú orí ni iyì arúgbó.

30 Ìgbájú ìgbámú àti ìfarapa máa ń mú ibi lọ,
    pàṣán sì máa ń ṣe àfọ̀mọ́ ibi ìkọ̀kọ̀ inú.

20 Wine(A) is a mocker(B) and beer a brawler;
    whoever is led astray(C) by them is not wise.(D)

A king’s wrath strikes terror like the roar of a lion;(E)
    those who anger him forfeit their lives.(F)

It is to one’s honor to avoid strife,
    but every fool(G) is quick to quarrel.(H)

Sluggards(I) do not plow in season;
    so at harvest time they look but find nothing.(J)

The purposes of a person’s heart are deep waters,(K)
    but one who has insight draws them out.

Many claim to have unfailing love,
    but a faithful person who can find?(L)

The righteous lead blameless lives;(M)
    blessed are their children after them.(N)

When a king sits on his throne to judge,(O)
    he winnows out all evil with his eyes.(P)

Who can say, “I have kept my heart pure;(Q)
    I am clean and without sin”?(R)

10 Differing weights and differing measures—
    the Lord detests them both.(S)

11 Even small children are known by their actions,
    so is their conduct really pure(T) and upright?

12 Ears that hear and eyes that see—
    the Lord has made them both.(U)

13 Do not love sleep or you will grow poor;(V)
    stay awake and you will have food to spare.

14 “It’s no good, it’s no good!” says the buyer—
    then goes off and boasts about the purchase.

15 Gold there is, and rubies in abundance,
    but lips that speak knowledge are a rare jewel.

16 Take the garment of one who puts up security for a stranger;
    hold it in pledge(W) if it is done for an outsider.(X)

17 Food gained by fraud tastes sweet,(Y)
    but one ends up with a mouth full of gravel.(Z)

18 Plans are established by seeking advice;
    so if you wage war, obtain guidance.(AA)

19 A gossip betrays a confidence;(AB)
    so avoid anyone who talks too much.

20 If someone curses their father or mother,(AC)
    their lamp will be snuffed out in pitch darkness.(AD)

21 An inheritance claimed too soon
    will not be blessed at the end.

22 Do not say, “I’ll pay you back for this wrong!”(AE)
    Wait for the Lord, and he will avenge you.(AF)

23 The Lord detests differing weights,
    and dishonest scales do not please him.(AG)

24 A person’s steps are directed(AH) by the Lord.(AI)
    How then can anyone understand their own way?(AJ)

25 It is a trap to dedicate something rashly
    and only later to consider one’s vows.(AK)

26 A wise king winnows out the wicked;
    he drives the threshing wheel over them.(AL)

27 The human spirit is[a] the lamp of the Lord(AM)
    that sheds light on one’s inmost being.(AN)

28 Love and faithfulness keep a king safe;
    through love(AO) his throne is made secure.(AP)

29 The glory of young men is their strength,
    gray hair the splendor of the old.(AQ)

30 Blows and wounds scrub(AR) away evil,
    and beatings(AS) purge the inmost being.

Footnotes

  1. Proverbs 20:27 Or A person’s words are