Add parallel Print Page Options

Saamu ti Dafidi. Nígbà ti ó sá fún ọmọ rẹ̀ Absalomu.

Olúwa, báwo ni àwọn ọ̀tá mi ṣe pọ̀ tó báyìí!
    Báwo ni àwọn ti ó dìde sí mi ṣe pọ̀ tó!
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ń sọ ní ti tèmi, pé
    “Ọlọ́run kò nígbà á là.” Sela.

Ṣùgbọ́n ìwọ ni asà yí mi ká, Olúwa;
    ìwọ fi ògo fún mi, ìwọ sì gbé orí mi sókè.
Olúwa ni mo kígbe sókè sí,
    ó sì dá mi lóhùn láti orí òkè mímọ́ rẹ̀ wá. Sela.

Èmi dùbúlẹ̀, mo sì sùn;
    mo sì tún padà jí, nítorí Olúwa ni ó ń gbé mi ró.
Èmi kì yóò bẹ̀rù ẹgbẹgbẹ̀rún ènìyàn
    tí wọ́n rọ̀gbà yí mi ká.

Dìde, Olúwa!
    Gbà mí, Ọlọ́run mi!
Lu gbogbo àwọn ọ̀tá mi ní àgbọ̀n;
    kí o sì ká eyín àwọn ènìyàn búburú.

Láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ìgbàlà ti wá.
    Kí ìbùkún rẹ wà lórí àwọn ènìyàn rẹ. Sela.