Add parallel Print Page Options

Òkè Olúwa

(A)Ní ọjọ́ ìkẹyìn

a ó fi òkè ilé Olúwa lélẹ̀ lórí àwọn òkè ńlá,
    a ó sì gbé e ga ju àwọn òkè kéékèèkéé lọ,
    àwọn ènìyàn yóò sì máa wọ̀ sínú rẹ̀.

Ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò wá,

wọn yóò sì wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á gòkè ńlá Olúwa,
    àti sí ilé Ọlọ́run Jakọbu
Òun yóò sì kọ́ wa ní ọ̀nà rẹ̀,
    kí àwa kí ó lè rìn ní ọ̀nà rẹ̀.”
Òfin yóò jáde láti Sioni wá,
    àti ọ̀rọ̀ Olúwa láti Jerusalẹmu.
Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn,
    yóò sì parí aáwọ̀ fún orílẹ̀-èdè alágbára jíjìn réré.
Wọn yóò sì fi idà wọn rọ ohun èlò ìtulẹ̀
    àti ọ̀kọ̀ wọn di dòjé
orílẹ̀-èdè kì yóò gbé idà sókè sí orílẹ̀-èdè mọ́,
    bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò kọ́ ogun jíjà mọ́.
(B)Ṣùgbọ́n olúkúlùkù yóò jókòó lábẹ́ àjàrà rẹ̀
    àti lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀,
ẹnìkan kì yóò sì dẹ́rùbà wọ́n,
    nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ̀rọ̀.
Gbogbo àwọn ènìyàn ń rìn,
    olúkúlùkù ni orúkọ ọlọ́run tirẹ̀,
ṣùgbọ́n àwa yóò máa rìn ní orúkọ Olúwa.
    Ọlọ́run wa láé àti láéláé.

Èrò Olúwa

“Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí,

“Èmi yóò kó àwọn arọ jọ;
    èmi yóò sì ṣà àwọn tí a lé kúrò ní ìlú jọ,
    àti àwọn ẹni tí èmi ti pọ́n lójú.
Èmi yóò dá àwọn arọ sí fún èyí tókù,
    èmi yóò sì sọ àwọn tí a lé kúrò ní ìlú di orílẹ̀-èdè alágbára.
Olúwa yóò sì jẹ ọba lórí wọn ní òkè ńlá Sioni
    láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé.
Ní ti ìwọ, ilé ìṣọ́ agbo àgùntàn,
    odi alágbára ọmọbìnrin Sioni,
a ó mú ìjọba ìṣáájú padà bọ̀ sípò fún un yín;
    ìjọba yóò sì wà sí ọ̀dọ̀ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.”

Kí ni ìwọ ha ń kígbe sókè sí nísinsin yìí?
    Ǹjẹ́ ìwọ kò ní ọba bí?
Àwọn ìgbìmọ̀ rẹ ṣègbé bí?
    Nítorí ìrora ti dì ọ́ mú bí obìnrin tí ń rọbí.
10 Máa yí síhìn-ín sọ́hùn-ún nínú ìrora,
    ìwọ obìnrin Sioni,
bí ẹni tí ń rọbí,
    nítorí nísinsin yìí ìwọ yóò jáde lọ kúrò ní ìlú,
ìwọ yóò sì máa gbé inú igbó.
    Ìwọ yóò lọ sí Babeli;
níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì ti rí ìgbàlà.
    Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti rà ọ́ padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ.

11 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè kó ara wọn jọ sí ọ.
    Wọ́n sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sọ ọ́ di àìmọ́,
    Ẹ jẹ́ kí ojú wa kí ó wo Sioni!”
12 Ṣùgbọ́n wọn kò mọ
    èrò inú Olúwa;
Bẹ́ẹ̀ ni òye ìmọ̀ rẹ̀ kò yé wọn,
    nítorí ó ti kó wọn jọ bí i ìtí sínú ìpakà.
13 “Dìde, kí ó sì máa pa ọkà ìwọ ọmọbìnrin Sioni,
    nítorí èmi yóò sọ ìwo rẹ̀ di irin,
èmi yóò sì sọ pátákò rẹ̀ di idẹ
    ìwọ yóò run ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pátápátá.”
Èmi yóò sì ya èrè wọn sọ́tọ̀ fún Olúwa
    àti ọrọ̀ wọn sí Olúwa gbogbo ayé.