Add parallel Print Page Options

Báwo ni wúrà ṣe sọ ògo dídán rẹ̀ nù,
    wúrà dídára di àìdán!
Òkúta ibi mímọ́ wá túká
    sí oríta gbogbo òpópó.

Báwo ni àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Sioni tí ó ṣe iyebíye,
    tí wọ́n fi wúrà dídára ṣe
wá dàbí ìkòkò amọ̀ lásán
    iṣẹ́ ọwọ́ amọ̀kòkò!

Àwọn ajáko pèsè ọmú wọn
    fún ìtọ́jú àwọn ọmọ wọn,
ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi wá láì lọ́kàn
    bí ògòǹgò ní aginjù.

Nítorí òǹgbẹ, ahọ́n àwọn ọmọ ọwọ́
    lẹ̀ mọ́ òkè ẹnu wọn;
àwọn ọmọdé bẹ̀bẹ̀ fún oúnjẹ
    Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó fi fún wọn.

Àwọn tí ó ń jẹ ohun dáradára
    di òtòṣì ní òpópó.
Àwọn tí a fi aṣọ dáradára wọ̀
    ni wọ́n sùn ní orí òkìtì eérú.

Ìjìyà àwọn ènìyàn mi
    tóbi ju ti Sodomu lọ,
tí a sí ní ipò ní òjijì
    láìsí ọwọ́ láti ràn án lọ́wọ́.

Ọmọ ọba ọkùnrin wọn mọ́ ju òjò-dídì,
    wọ́n sì funfun ju wàrà lọ
wọ́n ni ìtọ́jú bí iyùn pupa,
    ìrísí wọn dàbí safire.

Ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n dúdú ju èédú;
    wọn kò sì dá wọn mọ̀ ní òpópó.
Ara wọn hun mọ́ egungun;
    ó sì gbẹ bí igi gbígbẹ.

Àwọn tí ó kù nípasẹ̀ idà sàn
    ju àwọn tí ìyàn pa;
tí ó wọ àkísà ebi, tí ó ń ṣòfò
    fún àìní oúnjẹ láti inú pápá.

10 Pẹ̀lú ọwọ́ àwọn obìnrin aláàánú
    ni wọ́n ṣe ọmọ wọn jẹ
tí ó di oúnjẹ fún wọn
    nígbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run.

11 Olúwa ti fi ihò kíkún fún ìbínú rẹ̀;
    ó sì tú ìbínú gbígbóná rẹ̀ jáde.
Ó da iná ní Sioni
    tí ó jó ìpìlẹ̀ rẹ̀ run.

12 Àwọn ọba ayé kò gbàgbọ́,
    tàbí àwọn ènìyàn ayé,
wí pé àwọn ọ̀tá àti aninilára le wọ
    odi ìlú Jerusalẹmu.

13 Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn wòlíì
    àti àìṣedéédéé àwọn olórí àlùfáà,
tí ó ta ẹ̀jẹ̀ àwọn olódodo
    sílẹ̀ láàrín rẹ̀.

14 Nísinsin yìí wọ́n ń rìn kiri ní òpópó
    bí ọkùnrin tí ó fọ́jú.
Ẹ̀jẹ̀ ara wọn sọ wọ́n di àbàwọ́n
    tí kò sẹ́ni tó láyà láti fọwọ́ kan aṣọ wọn.

15 “Lọ kúrò! Ẹ̀yin di aláìmọ́!” ni àwọn ènìyàn ń kígbe sí wọn.
    “Ẹ lọ! Ẹ lọ! Ẹ má ṣe fọwọ́ kàn wá!”
Àwọn ènìyàn láàrín orílẹ̀-èdè wí pé,
    “Wọn kì yóò tẹ̀dó síbí mọ́.”

16 Olúwa ti tú wọn ká fúnrarẹ̀;
    kò sí bojútó wọn mọ́.
Kò sí ọ̀wọ̀ fún olórí àlùfáà mọ́,
    àti àánú fún àwọn àgbàgbà.

17 Síwájú sí i, ojú wa kùnà
    fún wíwo ìrànlọ́wọ́ asán;
láti orí ìṣọ́ wa ni à ń wò
    fún orílẹ̀-èdè tí kò le gbà wá là.

18 Wọ́n ń ṣọ́ wa kiri,
    àwa kò sì le rìn ní òpópó wa mọ́.
Òpin wa ti súnmọ́, ọjọ́ wa sì níye
    nítorí òpin wa ti dé.

19 Àwọn tí ń lé wa yára
    ju idì ojú ọ̀run lọ;
wọ́n lé wa ní gbogbo orí òkè
    wọ́n sì gẹ̀gùn dè wá ní aginjù.

20 Ẹni ààmì òróró Olúwa, èémí ìyè wa,
    ni wọ́n fi tàkúté wọn mú.
Àwa rò pé lábẹ́ òjìji rẹ̀
    ni àwa yóò máa gbé láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.

21 Ẹ yọ̀ kí inú yín sì dùn, ẹ̀yin ọmọbìnrin Edomu,
    ẹ̀yin tó ń gbé ní ilẹ̀ Usi.
Ṣùgbọ́n, a ó gbé ago náà kọjá sọ́dọ̀ rẹ pẹ̀lú;
    ìwọ yóò yó bí ọ̀mùtí, ìwọ yóò sì rìn ní ìhòhò.

22 Ìwọ ọmọbìnrin Sioni, ìjìyà rẹ yóò dópin;
    kò ní mú ìgbèkùn rẹ pẹ́ mọ́.
Ṣùgbọ́n, ìwọ ọmọbìnrin Edomu, yóò jẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ní yà
    yóò sì fi àìṣedéédéé rẹ hàn kedere.